Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

ÀWỌN Ọ̀DỌ́ BÉÈRÈ PÉ

Báwo Ni Eré Ìmárale Ṣe Lè Máa Wù Mí Ṣe?

Báwo Ni Eré Ìmárale Ṣe Lè Máa Wù Mí Ṣe?

 Kí nìdí tó fi yẹ kí n máa ṣe eré ìmárale?

 Láwọn orílẹ̀-èdè kan, àwọn ọ̀dọ́ kì í lo àkókò tó pọ̀ tó lẹ́nu eré ìmárale, ìyẹn ò sì dáa tó. Ó dájú pé ó nídìí tí Bíbélì náà fi sọ pé ‘àǹfààní wà nínú eré ìmárale.’ (1 Tímótì 4:8) Ẹ jẹ́ ká gbé àwọn ìdí náà yẹ̀ wò:

  •   Eré ìmárale máa mú kára tù ẹ́. Eré ìmárale máa ń jẹ́ kí ọpọlọ tú àwọn èròjà endorphins jáde sínú ara, ìyẹn àwọn èròjà tó máa ń mára tuni, tó sì máa ń jẹ́ kára ẹni yá gágá. Àwọn kan tiẹ̀ sọ pé egbòogi tí kì í jẹ́ kéèyàn sorí kọ́ ni eré ìmárale jẹ́.

     “Tí mo bá ti lọ sáré láàárọ̀ kùtù, ó máa ń jẹ́ kí n ṣiṣẹ́ dáadáa, mo sì tún máa ń gbádùn ara mi ṣúlẹ̀. Eré sísá máa ń jẹ́ kára mi yá gágá.”​—Regina.

  •   Eré ìmárale máa jẹ́ kí ìrísí ẹ dára sí i. Tó o bá ń ṣe eré ìmárale níwọ̀ntúnwọ̀nsì, wàá lókun sí i, ara ẹ á jí pépé sí i, ọkàn ẹ á sì túbọ̀ balẹ̀.

     “Lọ́dún kan sẹ́yìn, tí mo bá ń ṣe eré ìmárale kan tí wọ́n ń pè ní chin-ups, mi ò lè ṣe ju ẹyọ kan lọ, àmọ́ ní báyìí, mo ti lè ṣe mẹ́wàá. Inú mi dùn gan-an ni. Ohun tó múnú mi dùn jù lọ ni pé mo mọ̀ pé mò ń tọ́jú ara mi.”​—Olivia.

  •   Eré ìmárale máa jẹ́ kẹ́mìí ẹ gùn. Tára wa bá le, ó má jẹ́ ká lè mí dáadáa, á sì jẹ́ kí òpó ẹ̀jẹ̀ àti ọkàn wa máa ṣiṣẹ́ bó ṣe yẹ. Eré ìmárale tó máa ń jẹ́ kéèyàn lè mí dáadáa máa ń dènà àrùn inú òpó ẹ̀jẹ̀, àrùn yìí sì jẹ́ ọ̀kan lára ohun tó sábà máa ń pa àwọn èèyàn.

     “Tá a bá ń ṣeré ìmárale tó ń ṣara lóore déédéé, ṣe là ń fi han Ẹlẹ́dàá wa pé a mọyì ara tó fún wa.”​—Jessica.

 Ohun tó yẹ kó o fi sọ́kàn: Ọ̀pọ̀ àǹfààní la máa rí nísinsìnyí tá a bá ń ṣeré ìmárale, bá a sì ṣe ń dàgbà sí i, ara wa á máa jí pépé. Ọ̀dọ́bìnrin kan tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tonya sọ pé, “O ò ní kábàámọ̀ rárá tó o bá ṣeré ìmárale, bóyá tó o lọ sáré. Kò sígbà kan rí tí mo kábàámọ̀ lẹ́yìn tí mo ṣeré ìmárale tán.”

Bí ọkọ̀ tá a pa tì ṣe máa daṣẹ́ lẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ara wa ṣe máa rí tá ò bá ṣeré ìmárale

 Kí ló ń dí mi lọ́wọ́?

 Àwọn ìṣòro tó lè yọjú nìyí:

  •   Kò sídìí fún un. “Nígbà táwọn èèyàn bá ṣì kéré, wọ́n máa ń rò pé kò sí itú táwọn ò lè pa. Ó máa ń ṣòro fún wọn láti gbà pé ìgbà kan ń bọ tára ò ní le dáadáa mọ́. Wọ́n rò pé àwọn àgbàlagbà nìkan ló máa ń ṣàìsàn.”​—Sophia.

  •   Kò sáyè. “Ọwọ́ mi máa ń dí gan an torí náà mo ṣètò ara mi kí n lè máa ráyè jẹ oúnjẹ aṣaralóore kí n sì sùn, àmọ́ mi ò kí ń ráyè fún eré ìmárale.”​—Clarissa.

  •   Mi ò lówó ti màá san níbi tí wọ́n ti ń ṣeré ìmárale (gym). “Owó kékeré kọ́ lèèyàn máa ná kó tó lè nílera tó dáa, o gbọ́dọ̀ sanwó kó o tó lè lọ síbi tí wọ́n ti ń ṣeré ìmárale!”​—Gina.

 Ohun tó yẹ kó o ronú lé:

 Kí ló mú kó ṣòro fún jù lọ láti ṣeré ìmárale? O máa gba ìsapá kó o tó lè borí ìṣòro náà, àmọ́ àǹfààní tó o máa rí níbẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ ó jù bẹ́ẹ̀ lọ.

 Báwo ni mo ṣe lè mọ eré ìmárale tá a jẹ́ kí ìlera mi dáa?

 Àwọn àbá díẹ̀ rè é:

  •   Ìwọ fúnra ẹ̀ ni kó o sapá kí ìlera rẹ lè dáa sí i.​—Gálátíà 6:5.

  •   Má ṣàwáwí. (Oníwàásù 11:4) Bí àpẹẹrẹ, kò dìgbà tó o bá forúkọ sílẹ̀ níbi tí wọ́n ti ń ṣeré ìmárale (gym) kó o tó bẹ̀rẹ̀ sí ṣeré ìmárale. Wá eré ìmárale tó wù ẹ́, kó o sì máa ṣe é déédéé.

  •   Tó o bá fẹ́ mọ púpọ̀ sí i, o lè béèrè lọ́wọ́ ẹlòmíì nípa eré ìmárale tí wọ́n máa ń ṣe.​—Òwe 20:18.

  •   Ó yẹ kó o ní ìṣètò kan pàtó. Ní àfojúsùn, kó o sì máa kọ àṣeyọrí tó o ṣe sílẹ̀ kíyẹn lè fún ẹ níṣìírí.​—Òwe 21:5.

  •   Wá ẹni tí ẹ̀ẹ́ jọ máa ṣeré ìmárale. Tó o bá ní “irú ọ̀rẹ́ bẹ́ẹ̀” á fún ẹ níṣìírí láti máa ṣe é déédéé.​—Oníwàásù 4:​9, 10.

  •   Fi sọ́kàn pé ìfàsẹ́yìn lè ṣẹlẹ̀ lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, àmọ́ má jẹ́ kó sú ẹ.​—Òwe 24:10.

 Jẹ́ oníwọ̀ntúnwọ̀nsì

 Bíbélì gba àwọn ọkùnrin àti obìnrin níyànjú pé kí wọ́n “má ṣe jẹ́ aláṣejù.” (1 Tímótì 3:​2, 11) Tórí náà, jẹ́ oníwọ̀ntúnwọ̀nsì tó o bá ń ṣeré ìmárale. Àwọn tó máa ń ṣàṣejù nídìí eré ìmárale sábà máa ń pa ara wọn lára, àṣedànù ló sì máa ń jẹ́. Ọ̀dọ́bìnrin kan tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Julia sọ pé; “Tí ọkùnrin kan bá ní igẹ̀ tó tóbi gan-an, àmọ́ tí kò ní làákàyè, ó burẹ́wà ni.”

 Ó tún yẹ kó o yẹra fáwọn ìmọ̀ràn tó máa ń mú kéèyàn túbọ̀ tẹra mọ́ eré ìmárale lọ́nà tó gbòdì, wọ́n lè sọ pé: “Tó bá ti dà bíi pé o fẹ́ kú, ṣe mẹ́wàá sí i.” Irú ìmọ̀ràn bẹ́ẹ̀ lè pani lára, ó sì lè mú kéèyàn má fọkàn sí “àwọn ohun tó se pàtàkì jù” nígbèésí ayé.​—Fílípì 1:10.

 Láfikún síyẹn, ìmọ̀ràn tó ń mú kéèyàn túbọ̀ tẹra mọ́ eré ìmárale tún lè fa ìrẹ̀wẹ̀sì. Ọ̀dọ́bìnrin kan tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Vera ṣàkíyèsí pé: “Àwọn ọ̀dọ́bìnrin kan máa ń ní fọ́tò àwọn èèyàn tó wù wọ́n kí wọ́n jọ, wọ́n sì máa ń tún fọ́tò náà wò nígbà tí wọ́n bá rẹ̀wẹ̀sì. Àmọ́ tí wọ́n bá wá ríi pé ìrísí àwọn ò jọ tẹni tó wà nínú fọ́tò náà, ìrẹ̀wẹ̀sì máa dé. Ìlera rẹ ló yẹ kó ṣe pàtàkì sí ẹ ju ìrísí rẹ lọ.”