Sí Àwọn Ará Gálátíà 6:1-18

  • Ẹ máa bá ara yín gbé ẹrù (1-10)

    • Ohun tí èèyàn bá gbìn ló máa ká (7, 8)

  • Ìdádọ̀dọ́ kò ṣàǹfààní (11-16)

    • Ẹ̀dá tuntun (15)

  • Ìparí (17, 18)

6  Ẹ̀yin ará, tí ẹnì kan bá tiẹ̀ ṣi ẹsẹ̀ gbé kó tó mọ̀, kí ẹ̀yin tí ẹ kúnjú ìwọ̀n nípa tẹ̀mí sapá láti fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́* tọ́ ẹni náà sọ́nà.+ Àmọ́ kí ẹ máa kíyè sí ara yín lójú méjèèjì,+ kí a má bàa dẹ ẹ̀yin náà wò.+  Ẹ máa bá ara yín gbé ẹrù tó wúwo,+ nípa bẹ́ẹ̀, ẹ ó mú òfin Kristi ṣẹ.+  Tí ẹnì kan bá rò pé òun jẹ́ nǹkan kan nígbà tí kò jẹ́ nǹkan kan,+ ó ń tan ara rẹ̀ jẹ ni.  Àmọ́ kí kálukú máa yẹ ohun tó ń ṣe wò,+ nígbà náà, yóò láyọ̀ nítorí ohun tí òun fúnra rẹ̀ ṣe, kì í ṣe torí pé ó fi ara rẹ̀ wé ẹlòmíì.+  Torí kálukú ló máa ru ẹrù ara rẹ̀.*+  Yàtọ̀ síyẹn, kí ẹni tí à ń kọ́* ní ọ̀rọ̀ náà máa ṣàjọpín ohun rere gbogbo pẹ̀lú ẹni tó ń kọ́ni* ní irú ẹ̀kọ́ bẹ́ẹ̀.+  Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín jẹ: Ọlọ́run kò ṣeé tàn.* Nítorí ohun tí èèyàn bá gbìn, òun ló máa ká;+  torí pé ẹni tó bá ń fúnrúgbìn nítorí ara rẹ̀ máa ká ìdíbàjẹ́ látinú ara rẹ̀, àmọ́ ẹni tó bá ń fúnrúgbìn nítorí ẹ̀mí máa ká ìyè àìnípẹ̀kun látinú ẹ̀mí.+  Nítorí náà, ẹ má ṣe jẹ́ kí a jáwọ́ nínú ṣíṣe rere, torí tí àkókò bá tó, a máa kórè rẹ̀ tí a ò bá jẹ́ kó rẹ̀ wá.*+ 10  Tóò, nígbà tí a bá ti láǹfààní rẹ̀,* ẹ jẹ́ ká máa ṣe rere fún gbogbo èèyàn, àmọ́ ní pàtàkì fún àwọn tó bá wa tan nínú ìgbàgbọ́. 11  Ẹ wo àwọn lẹ́tà gàdàgbà tí mo fi kọ̀wé sí yín ní ọwọ́ ara mi. 12  Gbogbo àwọn tí ó fẹ́ kí àwọn èèyàn ní èrò tó dáa nípa wọn nínú ara,* ni àwọn tó fẹ́ sọ ọ́ di dandan fún yín pé kí ẹ dádọ̀dọ́,* wọ́n sì ń ṣe bẹ́ẹ̀ kí a má bàa ṣe inúnibíni sí wọn nítorí òpó igi oró* Kristi. 13  Nítorí àwọn tó ń dádọ̀dọ́* pàápàá kì í pa Òfin mọ́,+ àmọ́ wọ́n fẹ́ kí ẹ dádọ̀dọ́ kí wọ́n lè máa ti ara yín yangàn. 14  Ní tèmi, mi ò ní yangàn láé, àfi nípa òpó igi oró* Olúwa wa Jésù Kristi,+ ẹni tí a tipasẹ̀ rẹ̀ sọ ayé di òkú* lójú tèmi àti èmi lójú ti ayé. 15  Nítorí ìdádọ̀dọ́* tàbí àìdádọ̀dọ́* kọ́ ló ṣe pàtàkì,+ ẹ̀dá tuntun ló ṣe pàtàkì.+ 16  Ní ti gbogbo àwọn tó ń rìn létòlétò nínú ìlànà ìwà rere yìí, kí àlàáfíà àti àánú wà lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni, lórí Ísírẹ́lì Ọlọ́run.+ 17  Láti ìsinsìnyí lọ, kí ẹnikẹ́ni má dà mí láàmú mọ́, nítorí àpá ẹrú Jésù wà ní ara mi.+ 18  Ẹ̀yin ará, kí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Olúwa wa Jésù Kristi wà pẹ̀lú ẹ̀mí tí ẹ̀ ń fi hàn. Àmín.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Grk., “ẹ̀mí ìwà tútù.”
Tàbí “ṣe ojúṣe tirẹ̀.”
Tàbí “fi ọ̀rọ̀ ẹnu kọ́.”
Tàbí “fi ọ̀rọ̀ ẹnu kọ́ni.”
Ní Grk., “fi ṣe ẹlẹ́yà.”
Tàbí “juwọ́ sílẹ̀.”
Ní Grk., “ní àkókò tí a yàn kalẹ̀.”
Tàbí “tí wọ́n fẹ́ lẹ́wà lóde ara.”
Tàbí “kọlà.”
Tàbí “kọlà.”
Tàbí “kan ayé mọ́gi.”
Tàbí “ìkọlà.”
Tàbí “àìkọlà.”