Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

ÀWỌN Ọ̀DỌ́ BÉÈRÈ

Ṣé Dandan Ni Kí Wọ́n Ṣe Òfin Nínú Ilé?

Ṣé Dandan Ni Kí Wọ́n Ṣe Òfin Nínú Ilé?

 Ṣé òfin kan wà táwọn òbí ẹ ṣe nínú ilé tí ò bá ẹ lára mu? Àpilẹ̀kọ yìí àti ìwé tó o lè kọ èrò ẹ sí tó bá a wá máa jẹ́ kó o mọ bó o ṣe lè bá àwọn òbí ẹ sọ̀rọ̀ ní pa ẹ̀.

 Ojú tó yẹ kó o máa fi wò ó

 Àròsọ: Tó o bá ti kúrò nílé, o ti di ọ̀gá nìyẹn, kò sófin tó dè ẹ́ mọ́.

 Òótọ́ ọ̀rọ̀: Kò sọ́gbọ́n tó o fẹ́ dá sí i, wàá ṣì wà lábẹ́ àṣẹ àwọn kan tó o bá kúrò nílé. Ó lè jẹ́ ọ̀gá ẹ níbi iṣẹ́ tàbí ẹni tó gbà ẹ́ sílé, ó tiẹ̀ lè jẹ́ ìjọba. Danielle tó jẹ́ ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún (19) sọ pé, “Ìyàlẹ́nu ńlá ló máa jẹ fáwọn ọ̀dọ̀ tí òfin máa ń ni lára nígbà tí wọ́n wà nílé, wọ́n á rí i pé ọ̀rọ̀ ò rí báwọn ṣe rò ó nígbà tí wọ́n bá bẹ̀rẹ̀ sí í dá gbé.”

 Bíbélì sọ pé: “Jẹ́ onígbọràn sí àwọn ìjọba àti àwọn aláṣẹ.” (Títù 3:1) Tó o bá ń tẹ̀ lé òfin táwọn òbí ẹ ṣe, ó máa kọ́ ẹ bó o ṣe máa kojú àwọn nǹkan míì tó o bá bá pà dé lọ́jọ́ iwájú.

 Ohun tó o lè ṣe: Àǹfààní táwọn òfin yìí máa ṣe ẹ́ ni kó o máa wò. Ọ̀dọ́kùnrin kan tó ń jẹ́ Jeremy sọ́ pé: “Òfin táwọn òbí mi ṣe ràn mí lọ́wọ́ kí n lè mọ bí màá ṣe yan àwọn tó máa jẹ́ ọ̀rẹ́ mi àti bí màá ṣe máa lo àkókò mi. Kò tún jẹ́ kí n máa fi àkókó ṣòfò nídìí tẹlifíṣọ̀n, kí n sì máa jókòó ti géèmù ṣáá. Mò ń ráyè ṣe àwọn ohun tó n gbádùn mọ́ mi, tó sì ní láárí.”

 Ohun tó yẹ kó o ṣe

 Àmọ́ tó bá ń ṣe ẹ́ bíi pé àwọn òfin kan ò lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀ ńkọ́? Bí àpẹẹrẹ, ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Tamara sọ pé: “Nígbà kan, àwọn òbí mi gbà mí láyè láti rìnrìn àjò lọ́ sórílẹ̀-èdè míì. Àmọ́ ní báyìí tí mo ti pa dà sílé, wọn ò tiẹ̀ jẹ́ kí n gbé mọ́tò lọ sílùú kejì tó wà ní tòsí wa, ibi tó jẹ́ pé àti wa mọ́tò débẹ̀ ò ju ogún ìṣẹ́jú lọ!”

 Ká sọ pé irú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Tamara yìí ṣẹlẹ̀ sí ẹ, ṣó burú kó o bá àwọn òbí ẹ sọ̀rọ̀ lórí ọ̀rọ̀ náà? Kò sóhun tó burú níbẹ̀ rárá. Ìgbà tó o bá wọn sọ ọ́ àti bó o ṣe bá wọn sọ ọ́ ló ṣe pàtàkì.

 Ìgbà tó o bá wọn sọ ọ́. Ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Amanda sọ pé: “O gbọ́dọ̀ ti máa hùwà tó dáa, káwọn òbí ẹ̀ sì ti gbẹ̀rí ẹ jẹ́ kí ẹnu ẹ tó lè gbọ̀rọ̀ láti sọ fáwọn òbí ẹ pé kí wọ́n ṣàtúnṣe sí òfin kan.”

 Ọmọbìnrin kan tó ń jẹ́ Daria gbà pé òótọ́ lohun tí Amanda sọ. Ó sọ pé, “Ìgbà tí mọ́mì rí i pé mo ti ń gbọ́ràn sáwọn lẹ́nu dáadáa ni wọ́n tó bẹ̀rẹ̀ sí í ronú àti fagi lé àwọn òfin kan.” Má gbàgbé pé o ò lè fipá mú káwọn òbí ẹ fọkàn tán ẹ, ohun tó o bá ń ṣe ló máa mú kí wọ́n fọkàn tán ẹ.

Tó ò bá tẹ̀ lé àwọn òfin táwọn òbí ẹ ṣe nínú ilé, nǹkan ò ní lọ bó ṣe yẹ. Ṣe ló máa dà bí ohun tó máa ṣẹlẹ̀ táwọn tó ń wakọ̀ òfuurufú ò bá tẹ̀ lé òfin ìrìnnà

 Bíbélì sọ pé: “Pa àṣẹ baba rẹ mọ́, má sì ṣe ṣá òfin ìyá rẹ tì.” (Òwe 6:20) Tó o bá fi ohun ti ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yẹn sọ sílò, wàá lè mú káwọn òbí ẹ fọkàn tán ẹ̀, á sì rọrùn fún ẹ láti bá wọn sọ̀rọ̀.

 Bó o ṣe bá wọn sọ ọ́: Ọ̀dọ́kùnrin kan tó ń jẹ́ Steven sọ pé, “Téèyàn bá fẹ́ bá òbí ẹ̀ sọ̀rọ̀, ó máa ń dáa gan-an kéèyàn sọ̀rọ̀ lọ́nà pẹ̀lẹ́, kó sì fi hàn pé òun bọ̀wọ̀ fún wọn dípò kó máa jágbe mọ́ wọn tàbí kó máa ráhùn.”

 Daria tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́ẹ̀kàn fara mọ́ ohun tí Steven sọ, ó ní: “Tí mo bá tiẹ̀ ń bá mọ́mì mi jiyàn, kì í ran nǹkan. Ìgbà yẹn gan-an ni wọ́n tún wá lè mú káwọn òfin yẹn le sí i.”

  Bíbélì sọ pé: “Gbogbo ẹ̀mí rẹ̀ ni arìndìn ń tú jáde, ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́n a máa mú kí ó pa rọ́rọ́ títí dé ìkẹyìn.” (Òwe 29:11) Téèyàn bá ń kọ́ bí wọ́n ṣe ń pa nǹkan mọ́ra, inú ilé nìkan kọ́ ló ti máa ṣe é láǹfààní, á ràn án lọ́wọ́ níléèwé, níbí iṣẹ́, ní gbogbo ọ̀nà.

 Ohun tó o le ṣe: Máa ronú kó o tó sọ̀rọ̀. Téèyàn ò bá lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ra, tó wá da ìbínú bọlẹ̀, ó lè ba orúkọ rere tó ti ní tẹ́lẹ̀ pé ó jẹ́ ẹni tó ṣeé fọkàn tán jẹ́. Ìdí nìyẹn tí Bíbélì fi sọ pé “ẹni tí ó bá lọ́ra láti bínú pọ̀ yanturu ní ìfòyemọ̀.”— Òwe 14:29.

 Ìmọ̀ràn: Fi ìwé tó o lè kọ èrò ẹ sí tó bá àpilẹ̀kọ yìí wá ṣàyẹ̀wò òfin táwọn òbí ẹ ṣe, kó o sì ronú lé e lórí. Tó bá sì pọn dandan, ìwọ àtàwọn òbí ẹ lè jọ sọ̀rọ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí.