Sáàmù 31:1-24

  • Fi Jèhófà ṣe ibi ààbò

    • “Ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé” (5)

    • “Jèhófà, Ọlọ́run òtítọ́” (5)

    • Oore Ọlọ́run mà pọ̀ o (19)

Sí olùdarí. Orin Dáfídì. 31  Jèhófà, ìwọ ni mo fi ṣe ibi ààbò mi.+ Kí ojú má tì mí láé.+ Gbà mí sílẹ̀ nítorí òdodo rẹ.+   Tẹ́tí sí mi.* Tètè wá gbà mí sílẹ̀.+ Di àpáta ààbò fún mi,Ibi olódi láti gbà mí sílẹ̀.+   Ìwọ ni àpáta mi àti ibi ààbò mi;+Wàá darí mi,+ wàá sì ṣamọ̀nà mi, nítorí orúkọ rẹ.+   Wàá yọ mí kúrò nínú àwọ̀n tí wọ́n dẹ pa mọ́ dè mí,+Nítorí pé ìwọ ni odi ààbò mi.+   Ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé.+ O ti rà mí pa dà, Jèhófà, Ọlọ́run òtítọ́.*+   Mo kórìíra àwọn tó ń bọ òrìṣà asán, tí kò ní láárí,Àmọ́ ní tèmi, Jèhófà ni mo gbẹ́kẹ̀ lé.   Ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ yóò máa mú inú mi dùn gidigidi,Nítorí o ti rí ìpọ́njú mi;+O mọ ìdààmú ńlá tó bá mi.*   O kò fi mí lé ọ̀tá lọ́wọ́,Àmọ́ o mú kí n dúró ní ibi ààbò.*   Ṣojú rere sí mi, Jèhófà, torí mo wà nínú ìdààmú. Ìrora ti sọ ojú mi di bàìbàì,+ àárẹ̀ sì ti bá gbogbo ara mi.*+ 10  Ẹ̀dùn ọkàn+ ti gba ayé mi kan,Ìrora ni mo sì fi ń lo ọdún ayé mi.+ Agbára mi ń tán lọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi;Àárẹ̀ ti mú egungun mi.+ 11  Gbogbo àwọn ọ̀tá mi ń fi mí ṣẹ̀sín,+Pàápàá àwọn aládùúgbò mi. Mo ti di ẹni àríbẹ̀rù lójú àwọn ojúlùmọ̀ mi;Tí wọ́n bá rí mi lóde, ṣe ni wọ́n ń sá fún mi.+ 12  Mi ò sí lọ́kàn wọn mọ́,* wọ́n sì ti gbàgbé mi, àfi bíi pé mo ti kú;Mo dà bí ìkòkò tó fọ́. 13  Mo ti gbọ́ ọ̀pọ̀ àhesọ burúkú;Àwọn ohun ẹ̀rù yí mi ká.+ Nígbà tí wọ́n kóra jọ lé mi lórí,Wọ́n gbèrò láti gba ẹ̀mí* mi.+ 14  Àmọ́ Jèhófà, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀ lé.+ Mo sọ pé: “Ìwọ ni Ọlọ́run mi.”+ 15  Ọwọ́ rẹ ni ọjọ́ ayé* mi wà. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi àti lọ́wọ́ àwọn tó ń ṣe inúnibíni sí mi.+ 16  Mú kí ojú rẹ tàn sára ìránṣẹ́ rẹ.+ Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ gbà mí sílẹ̀. 17  Jèhófà, kí ojú má tì mí nígbà tí mo bá ké pè ọ́.+ Kí ojú ti àwọn ẹni burúkú;+Kí wọ́n dákẹ́ sínú Isà Òkú.*+ 18  Kí kẹ́kẹ́ pa mọ́ àwọn òpùrọ́ lẹ́nu,+Àwọn tó ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga àti ẹ̀gàn sí àwọn olódodo. 19  Oore rẹ mà pọ̀ o!+ O ti tò wọ́n jọ fún àwọn tó bẹ̀rù rẹ,+O sì ti fi wọ́n hàn lójú gbogbo èèyàn, nítorí àwọn tó fi ọ́ ṣe ibi ààbò.+ 20  Wàá fi wọ́n pa mọ́ sí ibi ìkọ̀kọ̀ tó wà níwájú rẹ+Kúrò nínú rìkíṣí àwọn èèyàn;Wàá fi wọ́n pa mọ́ sínú àgọ́ rẹKúrò lọ́wọ́ àwọn abanijẹ́.*+ 21  Ìyìn ni fún Jèhófà,Nítorí ó ti fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí mi lọ́nà àgbàyanu+ ní ìlú tí ọ̀tá dó tì.+ 22  Ní tèmi, jìnnìjìnnì bò mí, mo sì sọ pé: “Màá ṣègbé níwájú rẹ.”+ Àmọ́ nígbà tí mo ké pè ọ́, o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún ìrànlọ́wọ́.+ 23  Ẹ nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ adúróṣinṣin sí i!+ Jèhófà ń dáàbò bo àwọn olóòótọ́,+Àmọ́ ó máa ń san èrè tó kún rẹ́rẹ́ fún àwọn tó bá ń gbéra ga.+ 24  Ẹ jẹ́ onígboyà, kí ẹ sì mọ́kàn le,+Gbogbo ẹ̀yin tí ẹ̀ ń dúró de Jèhófà.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “Bẹ̀rẹ̀ kí o sì fetí sí mi.”
Tàbí “Ọlọ́run olóòótọ́.”
Tàbí “ìdààmú ọkàn mi.”
Tàbí “ibi tó láyè fífẹ̀.”
Tàbí “ọkàn mi àti ikùn mi.”
Tàbí “Wọn ò fiyè sí mi mọ́.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “àwọn àkókò.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Ní Héb., “lọ́wọ́ ìjà ahọ́n.”