Sáàmù 100:1-5

  • Ẹ fi ọpẹ́ fún Ẹlẹ́dàá

    • “Ẹ fi ayọ̀ sin Jèhófà” (2)

    • ‘Ọlọ́run ló dá wa’ (3)

Orin ọpẹ́. 100  Ẹ kígbe ìṣẹ́gun sí Jèhófà, gbogbo ayé.+   Ẹ fi ayọ̀ sin Jèhófà.+ Ẹ fi igbe ayọ̀ wá síwájú rẹ̀.   Kí ẹ mọ̀* pé Jèhófà ni Ọlọ́run.+ Òun ló dá wa, tirẹ̀ la sì jẹ́.*+ Àwa ni èèyàn rẹ̀ àti àgùntàn ibi ìjẹko rẹ̀.+   Ẹ wọlé sínú àwọn ẹnubodè rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́,+Sínú àwọn àgbàlá rẹ̀ pẹ̀lú ìyìn.+ Ẹ fi ọpẹ́ fún un; ẹ yin orúkọ rẹ̀.+   Nítorí Jèhófà jẹ́ ẹni rere;+Ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí láé,Òtítọ́ rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “gbà.”
Tàbí kó jẹ́, “kì í ṣe àwa fúnra wa.”