Sáàmù 23:1-6

  • “Jèhófà ni Olùṣọ́ Àgùntàn mi”

    • “Èmi kì yóò ṣaláìní” (1)

    • “Ó tù mí lára” (3)

    • “Ife mi kún dáadáa” (5)

Orin Dáfídì. 23  Jèhófà ni Olùṣọ́ Àgùntàn mi.+ Èmi kì yóò ṣaláìní.+   Ó mú mi dùbúlẹ̀ ní ibi ìjẹko tútù;Ó darí mi sí àwọn ibi ìsinmi tó lómi dáadáa.*+   Ó tù mí* lára.+ Ó darí mi ní ipa ọ̀nà òdodo nítorí orúkọ rẹ̀.+   Bí mo tilẹ̀ ń rìn nínú àfonífojì tó ṣókùnkùn biribiri,+Mi ò bẹ̀rù ewukéwu,+Nítorí o wà pẹ̀lú mi;+Ọ̀gọ* rẹ àti ọ̀pá rẹ ń fi mí lọ́kàn balẹ̀.*   O tẹ́ tábìlì fún mi níwájú àwọn ọ̀tá mi.+ O fi òróró pa orí mi;*+Ife mi kún dáadáa.+   Dájúdájú, ire àti ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn ní gbogbo ọjọ́ ayé mi,+Èmi yóò sì máa gbé inú ilé Jèhófà ní gbogbo ọjọ́ ayé mi.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí kó jẹ́, “síbi omi tó pa rọ́rọ́.”
Tàbí “Ó tu ọkàn mi.”
Tàbí “ń tù mí nínú.”
Ìyẹn, ọ̀pá tí orí rẹ̀ rí rubutu.
Tàbí “tu orí mi lára.”