Sí Àwọn Ará Róòmù 6:1-23

  • Ìgbé ayé ọ̀tun nípasẹ̀ batisí sínú Kristi (1-11)

  • Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ jọba nínú ara yín (12-14)

  • Láti ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ sí ẹrú Ọlọ́run (15-23)

    • Èrè ẹ̀ṣẹ̀ ni ikú; Ẹ̀bùn Ọlọ́run ni ìyè (23)

6  Kí ni ká wá sọ? Ṣé ká máa dá ẹ̀ṣẹ̀ lọ kí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí lè máa pọ̀ sí i ni?  Ká má ri! Bó ṣe jẹ́ pé a ti bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀,+ ṣé ó yẹ kó ṣì tún máa darí wa?+  Àbí ẹ ò mọ̀ pé gbogbo wa tí a ti batisí sínú Kristi Jésù+ la ti batisí sínú ikú rẹ̀?+  Nítorí náà, a sin wá pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ nípasẹ̀ ìbatisí wa sínú ikú rẹ̀,+ kí ó lè jẹ́ pé bí a ti gbé Kristi dìde kúrò nínú ikú nípasẹ̀ ògo Baba, kí àwa náà lè máa gbé ìgbé ayé ọ̀tun.+  Bí a ṣe wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú rẹ̀ lọ́nà tó gbà kú,+ ó dájú pé a ó tún lè wà níṣọ̀kan pẹ̀lú rẹ̀ lọ́nà tó gbà jíǹde.+  Torí a mọ̀ pé a ti kan ìwà wa àtijọ́ mọ́gi* pẹ̀lú rẹ̀,+ kí ara ẹ̀ṣẹ̀ wa lè di aláìlágbára,+ kí a má ṣe jẹ́ ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ mọ́.+  Nítorí ẹni tó bá ti kú ni a ti dá sílẹ̀ pátápátá* kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.  Yàtọ̀ síyẹn, tí a bá ti kú pẹ̀lú Kristi, a gbà gbọ́ pé a ó tún wà láàyè pẹ̀lú rẹ̀.  Torí a mọ̀ pé ní báyìí tí a ti gbé Kristi dìde kúrò nínú ikú,+ kò ní kú mọ́;+ ikú kò lágbára lórí rẹ̀ mọ́. 10  Nítorí ikú tó kú jẹ́ láti mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò,* ó kú lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní kú mọ́ láé,+ àmọ́ ìgbé ayé tó ń gbé jẹ́ láti máa ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run. 11  Bákan náà, kí ẹ gbà pé ẹ ti kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ́ ẹ wà láàyè nínú Ọlọ́run nípasẹ̀ Kristi Jésù.+ 12  Nítorí náà, ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ máa jọba lọ nínú ara kíkú yín,+ tí ẹ ó fi máa ṣe ìfẹ́ ti ara. 13  Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ máa lo àwọn ẹ̀yà ara* yín bí ohun ìjà àìṣòdodo mọ́, àmọ́ ẹ fi ara yín fún Ọlọ́run bí àwọn tí a gbé dìde látinú ikú, kí ẹ sì fi àwọn ẹ̀yà ara* yín fún Ọlọ́run bí ohun ìjà òdodo.+ 14  Torí ẹ̀ṣẹ̀ kò gbọ́dọ̀ jẹ ọ̀gá lórí yín, nítorí ẹ ò sí lábẹ́ òfin,+ àmọ́ ẹ wà lábẹ́ inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí.+ 15  Kí ló wá kàn? Ṣé ká wá máa dẹ́ṣẹ̀ torí pé a ò sí lábẹ́ òfin, àmọ́ a wà lábẹ́ inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí ni?+ Ká má ri! 16  Ṣé ẹ ò mọ̀ pé tí ẹ bá fi ara yín ṣe ẹrú tó ń ṣègbọràn fún ẹnì kan, ẹrú lẹ jẹ́ fún ẹni tí ẹ̀ ń ṣègbọràn sí,+ ì báà jẹ́ fún ẹ̀ṣẹ̀+ tó ń yọrí sí ikú+ tàbí fún ìgbọràn tó ń yọrí sí òdodo? 17  Àmọ́ ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run pé bí ẹ tiẹ̀ jẹ́ ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ nígbà kan rí, ẹ ti ń ṣègbọràn látọkàn wá sí ẹ̀kọ́ tí a fi lé yín lọ́wọ́. 18  Bẹ́ẹ̀ ni, àtìgbà tí a ti dá yín sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀+ ni ẹ ti di ẹrú òdodo.+ 19  Mò ń lo ọ̀rọ̀ tí èèyàn lè tètè lóye nítorí àìlera ara yín; torí bí ẹ ṣe fi àwọn ẹ̀yà ara yín ṣe ẹrú ìwà àìmọ́ àti ìwà tí kò bófin mu tó ń yọrí sí ìwà tí kò bófin mu, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ fi àwọn ẹ̀yà ara yín ṣe ẹrú ní báyìí fún òdodo tó ń yọrí sí ìjẹ́mímọ́.+ 20  Torí nígbà tí ẹ jẹ́ ẹrú ẹ̀ṣẹ̀, ẹ ò sí lábẹ́ òdodo. 21  Kí wá ni èso tí ẹ̀ ń mú jáde nígbà yẹn? Àwọn nǹkan tó ń tì yín lójú ní báyìí. Nítorí ikú ni òpin àwọn nǹkan yẹn.+ 22  Àmọ́ ní báyìí tí a ti dá yín sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀, tí ẹ sì ti di ẹrú Ọlọ́run, ẹ̀ ń so èso yín lọ́nà ìjẹ́mímọ́,+ ìyè àìnípẹ̀kun sì ni òpin rẹ̀.+ 23  Nítorí ikú ni èrè* ẹ̀ṣẹ̀,+ àmọ́ ìyè àìnípẹ̀kun ni ẹ̀bùn tí Ọlọ́run ń fúnni+ nípasẹ̀ Kristi Jésù Olúwa wa.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “mọ́ òpó igi.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “tú sílẹ̀; dárí jì.”
Ìyẹn, láti pa ẹ̀ṣẹ̀ rẹ́.
Tàbí “ara.”
Tàbí “ara.”
Ní Grk., “owó iṣẹ́.”