Sí Àwọn Ará Róòmù 5:1-21

  • Èèyàn pa dà bá Ọlọ́run rẹ́ nípasẹ̀ Kristi (1-11)

  • Ikú wá nípasẹ̀ Ádámù, ìyè wá nípasẹ̀ Kristi (12-21)

    • Ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú tàn dé ọ̀dọ̀ gbogbo èèyàn (12)

    • Ìwà òdodo kan (18)

5  Tóò, ní báyìí tí a ti pè wá ní olódodo nítorí ìgbàgbọ́,+ ẹ jẹ́ kí a máa gbádùn àlàáfíà* pẹ̀lú Ọlọ́run nípasẹ̀ Olúwa wa Jésù Kristi,+  ẹni tó mú ká rí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí tí à ń gbádùn báyìí gbà nípasẹ̀ ìgbàgbọ́;+ ẹ jẹ́ kí a máa yọ̀,* lórí ìrètí ògo Ọlọ́run.  Kì í ṣe ìyẹn nìkan, àmọ́ ẹ jẹ́ ká máa yọ̀* nígbà tí a bá wà nínú ìpọ́njú,+ torí a mọ̀ pé ìpọ́njú ń mú ìfaradà wá;+  ìfaradà ní tirẹ̀ ń mú ìtẹ́wọ́gbà wá;+ ìtẹ́wọ́gbà sì ń mú ìrètí wá,+  ìrètí kì í sì í yọrí sí ìjákulẹ̀;+ nítorí pé a ti tú ìfẹ́ Ọlọ́run jáde sínú ọkàn wa nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́, èyí tí a fún wa.+  Torí, ní tòótọ́, nígbà tí a ṣì jẹ́ aláìlera,+ Kristi kú fún àwọn tí kò ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ní àkókò tí a yàn.  Bóyá ni ẹnì kan á lè kú nítorí olódodo; síbẹ̀, ẹnì kan lè ṣe tán láti kú nítorí ẹni rere.  Àmọ́ Ọlọ́run dámọ̀ràn ìfẹ́ rẹ̀ fún wa ní ti pé, nígbà tí a ṣì jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, Kristi kú fún wa.+  Nígbà tí a sì ti wá pè wá ní olódodo nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ rẹ̀,+ ó dájú pé ó máa mú kí a bọ́ lọ́wọ́ ìrunú.+ 10  Torí tó bá jẹ́ pé nígbà tí a jẹ́ ọ̀tá, ikú Ọmọ Ọlọ́run mú wa pa dà bá a rẹ́,+ ǹjẹ́ ààyè rẹ̀ kò ní mú ká rí ìgbàlà ní báyìí tí a ti pa dà bá a rẹ́? 11  Kì í ṣe ìyẹn nìkan, àmọ́ a tún ń yọ̀ nínú Ọlọ́run nípasẹ̀ Olúwa wa Jésù Kristi, ẹni tó mú ká rí ìpadàrẹ́ gbà ní báyìí.+ 12  Ìdí nìyẹn tó fi jẹ́ pé, bí ẹ̀ṣẹ̀ ṣe tipasẹ̀ ẹnì kan wọ ayé, tí ikú sì wá nípasẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,+ bẹ́ẹ̀ ni ikú ṣe tàn dé ọ̀dọ̀ gbogbo èèyàn torí pé gbogbo wọn ti dẹ́ṣẹ̀+—. 13  Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ti wà ní ayé kí Òfin tó dé, àmọ́ a kì í ka ẹ̀ṣẹ̀ sí ẹnikẹ́ni lọ́rùn nígbà tí kò sí òfin.+ 14  Síbẹ̀, ikú jọba láti ọ̀dọ̀ Ádámù títí dé ọ̀dọ̀ Mósè, àní lórí àwọn tí kò dẹ́ṣẹ̀ bíi ti Ádámù, ẹni tó fara jọ ẹni tó ń bọ̀.+ 15  Àmọ́ ẹ̀bùn náà ò rí bí àṣemáṣe. Torí bó ṣe jẹ́ pé nípa àṣemáṣe ọkùnrin kan ni ọ̀pọ̀ èèyàn fi kú, ẹ wo bí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run àti ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ rẹ̀ nípasẹ̀ inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí ọkùnrin kan,+ ìyẹn Jésù Kristi, ṣe ṣe ọ̀pọ̀ èèyàn láǹfààní!*+ 16  Bákan náà, àǹfààní tí ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí mú wá kì í ṣe ohun kan náà pẹ̀lú ohun tí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin kan mú wá.+ Nítorí ìdájọ́ tó tẹ̀ lé àṣemáṣe kan yọrí sí ìdálẹ́bi ọ̀pọ̀ èèyàn,+ àmọ́ ẹ̀bùn tó tẹ̀ lé ọ̀pọ̀ àṣemáṣe yọrí sí pípè wọ́n ní olódodo.+ 17  Torí tí àṣemáṣe ọkùnrin kan bá mú kí ikú jọba nípasẹ̀ ẹni náà,+ ǹjẹ́ àwọn tó gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ òdodo+ kò ní jọba+ nínú ìyè nípasẹ̀ èèyàn kan, ìyẹn Jésù Kristi?+ 18  Nítorí náà, bó ṣe jẹ́ pé àṣemáṣe kan ló yọrí sí ìdálẹ́bi onírúurú èèyàn,+ bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe jẹ́ pé ìwà òdodo kan ló mú ká pe onírúurú èèyàn+ ní olódodo fún ìyè.+ 19  Nítorí bó ṣe jẹ́ pé àìgbọràn èèyàn kan ló mú kí ọ̀pọ̀ èèyàn di ẹlẹ́ṣẹ̀,+ bẹ́ẹ̀ náà ni ìgbọràn èèyàn kan á ṣe mú kí ọ̀pọ̀ èèyàn di olódodo.+ 20  Tóò, Òfin wọlé wá kí àṣemáṣe lè pọ̀ sí i.+ Àmọ́ níbi tí ẹ̀ṣẹ̀ bá ti pọ̀, inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí á pọ̀ jù ú lọ. 21  Nítorí kí ni? Kí ó lè jẹ́ pé bí ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú ṣe jọba,+ kí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí lè jọba nípasẹ̀ òdodo, kí ó sì yọrí sí ìyè àìnípẹ̀kun nípasẹ̀ Jésù Kristi Olúwa wa.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí kó jẹ́, “a wà ní àlàáfíà.”
Tàbí kó jẹ́, “à ń yọ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “à ń yọ̀.”
Tàbí “ṣe ṣàn dé ọ̀dọ̀ ọ̀pọ̀ èèyàn!”