Sí Àwọn Ará Gálátíà 5:1-26
5 Kristi ti dá wa sílẹ̀ ká lè ní irú òmìnira yìí. Nítorí náà, ẹ dúró gbọn-in,+ ẹ má sì tọrùn bọ àjàgà ẹrú mọ́.+
2 Ẹ wò ó! Èmi, Pọ́ọ̀lù, ń sọ fún yín pé tí ẹ bá dádọ̀dọ́,* Kristi ò ní ṣe yín láǹfààní kankan.+
3 Mo tún jẹ́rìí sí i pé dandan ni fún gbogbo ẹni tó bá dádọ̀dọ́* láti pa gbogbo Òfin mọ́.+
4 Ẹ ti kúrò lọ́dọ̀ Kristi, ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ kí a pè yín ní olódodo nípasẹ̀ òfin;+ ẹ ti yà kúrò nínú inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí rẹ̀.
5 Ní tiwa, nínú ẹ̀mí, à ń dúró de òdodo tí à ń retí lójú méjèèjì, èyí tó ń wá látinú ìgbàgbọ́.
6 Torí nínú Kristi Jésù, ìdádọ̀dọ́* tàbí àìdádọ̀dọ́* kò ṣàǹfààní,+ ìgbàgbọ́ tó ń ṣiṣẹ́ nípasẹ̀ ìfẹ́ ló ṣàǹfààní.
7 Ẹ ti ń sáré dáadáa tẹ́lẹ̀.+ Ta ló dí yín lọ́wọ́ kí ẹ má ṣègbọràn sí òtítọ́ mọ́?
8 Irú èrò tí wọ́n fi yí yín lọ́kàn pa dà yìí kò wá látọ̀dọ̀ Ẹni tó ń pè yín.
9 Ìwúkàrà díẹ̀ ló ń mú gbogbo ìṣùpọ̀ wú.+
10 Ọkàn mi balẹ̀ pé ẹ̀yin tí ẹ wà nínú Olúwa+ kò ní ronú lọ́nà míì; àmọ́, ẹni tó ń dá wàhálà sílẹ̀ fún yín,+ ẹnì yòówù kó jẹ́, yóò gba ìdájọ́ tó tọ́ sí i.
11 Ní tèmi, ẹ̀yin ará, tí mo bá ṣì ń wàásù ìdádọ̀dọ́,* kí ló dé tí wọ́n tún ń ṣe inúnibíni sí mi? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, òpó igi oró*+ kì í ṣe ohun ìkọ̀sẹ̀ mọ́ fún àwọn tó ń ta kò mí.
12 Ó wù mí kí àwọn tó fẹ́ da àárín yín rú tẹ ara wọn lọ́dàá.*
13 Ẹ̀yin ará, a pè yín kí ẹ lè ní òmìnira; kìkì pé kí ẹ má ṣe lo òmìnira yìí láti máa ṣe ìfẹ́ ti ara,+ àmọ́ ẹ jẹ́ kí ìfẹ́ máa mú kí ẹ sin ara yín bí ẹrú.+
14 Nítorí a ti mú gbogbo Òfin ṣẹ nínú* àṣẹ kan ṣoṣo, tó sọ pé: “Kí o nífẹ̀ẹ́ ọmọnìkejì rẹ bí ara rẹ.”+
15 Tí ẹ bá wá ń bu ara yín jẹ, tí ẹ sì ń fa ara yín ya,+ ẹ ṣọ́ra kí ẹ má bàa pa ara yín run.+
16 Àmọ́ mo sọ pé, Ẹ máa rìn nípa ẹ̀mí,+ ẹ kò sì ní ṣe ìfẹ́ ti ara rárá.+
17 Nítorí ohun tí ara ń fẹ́ lòdì sí ohun tí ẹ̀mí ń fẹ́, ẹ̀mí sì lòdì sí ara; àwọn méjèèjì ta ko ara wọn, ìdí nìyẹn tí ẹ kò fi lè ṣe ohun tí ẹ fẹ́ ṣe.+
18 Yàtọ̀ síyẹn, tí ẹ̀mí bá ń darí yín, ẹ kò sí lábẹ́ òfin.
19 Àwọn iṣẹ́ ti ara hàn kedere, àwọn sì ni ìṣekúṣe,*+ ìwà àìmọ́, ìwà àìnítìjú,*+
20 ìbọ̀rìṣà, ìbẹ́mìílò,*+ ìkórìíra, wàhálà, owú, inú fùfù, awuyewuye, ìpínyà, ẹ̀ya ìsìn,
21 ìlara, ìmutíyó,+ àwọn àríyá aláriwo àti irú àwọn nǹkan yìí.+ Mò ń kìlọ̀ fún yín ṣáájú nípa àwọn nǹkan yìí, lọ́nà kan náà tí mo gbà kìlọ̀ fún yín tẹ́lẹ̀, pé àwọn tó bá ń ṣe àwọn nǹkan yìí kò ní jogún Ìjọba Ọlọ́run.+
22 Àmọ́, èso ti ẹ̀mí ni ìfẹ́, ayọ̀, àlàáfíà, sùúrù,* inú rere, ìwà rere,+ ìgbàgbọ́,
23 ìwà tútù, ìkóra-ẹni-níjàánu.+ Kò sí òfin kankan tó lòdì sí irú àwọn nǹkan yìí.
24 Yàtọ̀ síyẹn, àwọn tó jẹ́ ti Kristi Jésù ti kan ẹran ara mọ́gi* pẹ̀lú ohun tí ẹran ara ń fẹ́ àti ohun tó ń wù ú.+
25 Tí a bá wà láàyè nípa ẹ̀mí, ẹ jẹ́ kí a máa rìn létòlétò nípa ẹ̀mí.+
26 Ẹ má ṣe jẹ́ kí a di agbéraga,+ kí a má ṣe máa bá ara wa díje,+ kí a má sì máa jowú ara wa.
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Tàbí “kọlà.”
^ Tàbí “kọlà.”
^ Tàbí “ìkọlà.”
^ Tàbí “àìkọlà.”
^ Tàbí “ìkọlà.”
^ Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
^ Tàbí “di ìwẹ̀fà,” kí wọ́n tipa bẹ́ẹ̀ di ẹni tí kò kúnjú ìwọ̀n láti tẹ̀ lé òfin tí wọ́n fọwọ́ sí.
^ Tàbí kó jẹ́, “kó gbogbo Òfin jọ sínú.”
^ Lédè Gíríìkì, por·neiʹa. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
^ Tàbí “ìwà ọ̀dájú.” Ní Gíríìkì, a·selʹgei·a. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
^ Tàbí “iṣẹ́ oṣó; lílo oògùn olóró.”
^ Tàbí “ìpamọ́ra.”
^ Tàbí “mọ́ òpó igi.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.