Àkọsílẹ̀ Lúùkù 11:1-54

  • Bí o ṣe lè gbàdúrà (1-13)

    • Àdúrà àwòkọ́ṣe (2-4)

  • Ó fi ìka Ọlọ́run lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde (14-23)

  • Ẹ̀mí àìmọ́ pa dà wá (24-26)

  • Ayọ̀ tòótọ́ (27, 28)

  • Àmì Jónà (29-32)

  • Fìtílà ara (33-36)

  • Àwọn ẹlẹ́sìn tó ń ṣe àgàbàgebè gbé (37-54)

11  Ní báyìí, ó wà ní ibì kan tó ti ń gbàdúrà, nígbà tó sì ṣe tán, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ sọ fún un pé: “Olúwa, kọ́ wa bí a ṣe máa gbàdúrà, bí Jòhánù náà ṣe kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀.”  Torí náà, ó sọ fún wọn pé: “Nígbàkigbà tí ẹ bá ń gbàdúrà, ẹ sọ pé: ‘Baba, kí orúkọ rẹ di mímọ́.*+ Kí ìjọba rẹ dé.+  Fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa bí a ṣe nílò rẹ̀ lọ́jọ́ kọ̀ọ̀kan.+  Kí o sì dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá,+ torí àwa náà máa ń dárí ji gbogbo ẹni tó jẹ wá ní gbèsè;+ má sì mú wa wá sínú ìdẹwò.’”+  Ó wá sọ fún wọn pé: “Ká sọ pé ọ̀kan nínú yín ní ọ̀rẹ́ kan, o wá lọ bá a ní ọ̀gànjọ́ òru, o sì sọ fún un pé, ‘Ọ̀rẹ́, yá mi ní búrẹ́dì mẹ́ta,  torí pé ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣẹ̀ṣẹ̀ dé sọ́dọ̀ mi láti ìrìn àjò, mi ò sì ní nǹkan kan tí mo lè fún un.’  Àmọ́ ẹni yẹn fèsì látinú ilé, ó ní: ‘Yéé dà mí láàmú. Mo ti ti ilẹ̀kùn, àwọn ọmọ mi kéékèèké sì wà lọ́dọ̀ mi lórí ibùsùn. Mi ò lè dìde wá fún ọ ní ohunkóhun.’  Mò ń sọ fún yín, bí kò bá tiẹ̀ ní dìde, kó sì fún un ní nǹkan kan torí pé ó jẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó dájú pé torí pé ó ń fi ìgboyà béèrè léraléra,+ ó máa dìde, ó sì máa fún un ní ohunkóhun tó bá nílò.  Torí náà, mò ń sọ fún yín, ẹ máa béèrè,+ a sì máa fún yín; ẹ máa wá kiri, ẹ sì máa rí; ẹ máa kan ilẹ̀kùn, a sì máa ṣí i fún yín.+ 10  Torí gbogbo ẹni tó bá ń béèrè máa rí gbà,+ gbogbo ẹni tó bá ń wá kiri máa rí, gbogbo ẹni tó bá sì ń kan ilẹ̀kùn la máa ṣí i fún. 11  Ká sòótọ́, bàbá wo ló wà láàárín yín tó jẹ́ pé, tí ọmọ rẹ̀ bá béèrè ẹja, ó máa fún un ní ejò dípò ẹja?+ 12  Tàbí tó bá tún béèrè ẹyin, tó máa fún un ní àkekèé? 13  Torí náà, tí ẹ̀yin bá mọ bí ẹ ṣe ń fún àwọn ọmọ yín ní ẹ̀bùn tó dáa, bó tiẹ̀ jẹ́ pé ẹni burúkú ni yín, mélòómélòó wá ni Baba yín tó wà ní ọ̀run, ó máa fi ẹ̀mí mímọ́ fún àwọn tó ń béèrè lọ́wọ́ rẹ̀!”+ 14  Lẹ́yìn náà, ó lé ẹ̀mí èṣù tí kò jẹ́ kó lè sọ̀rọ̀ jáde.+ Lẹ́yìn tí ẹ̀mí èṣù náà jáde, ọkùnrin tí kò lè sọ̀rọ̀ náà sọ̀rọ̀, ẹnu sì ya àwọn èrò tó wà níbẹ̀.+ 15  Àmọ́ àwọn kan nínú wọn sọ pé: “Agbára Béélísébúbù,* alákòóso àwọn ẹ̀mí èṣù, ló fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.”+ 16  Kí àwọn míì sì lè dán an wò, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún un pé kó fi àmì kan+ láti ọ̀run han àwọn. 17  Ó mọ ohun tí wọ́n ń rò,+ ó wá sọ fún wọn pé: “Gbogbo ìjọba tó bá pínyà sí ara rẹ̀ máa pa run, ilé tó bá sì pínyà sí ara rẹ̀ máa wó. 18  Lọ́nà kan náà, tí Sátánì náà bá pínyà sí ara rẹ̀, báwo ni ìjọba rẹ̀ ṣe máa dúró? Torí ẹ sọ pé Béélísébúbù ni mo fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde. 19  Tó bá jẹ́ agbára Béélísébúbù ni mo fi ń lé ẹ̀mí èṣù jáde, agbára ta ni àwọn ọmọ yín fi ń lé wọn jáde? Ìdí nìyí tí wọ́n fi máa jẹ́ adájọ́ yín. 20  Àmọ́ tó bá jẹ́ ìka Ọlọ́run + ni mo fi ń lé ẹ̀mí èṣù jáde, Ìjọba Ọlọ́run ti dé bá yín lójijì lóòótọ́.+ 21  Tí ọkùnrin alágbára kan, tó dira ogun dáadáa, bá ń ṣọ́ ààfin rẹ̀, kò sóhun tó máa ṣe àwọn ohun ìní rẹ̀. 22  Àmọ́ tí ẹnì kan tó lágbára jù ú lọ bá wá gbéjà kò ó, tó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ẹni yẹn máa kó gbogbo ohun ìjà rẹ̀ tó gbẹ́kẹ̀ lé lọ, á sì pín àwọn ohun tó kó lọ́dọ̀ rẹ̀. 23  Ẹnikẹ́ni tí kò bá sí lọ́dọ̀ mi ń ta kò mí, ẹnikẹ́ni tí kò bá sì dara pọ̀ mọ́ mi ń fọ́n ká.+ 24  “Tí ẹ̀mí àìmọ́ kan bá jáde nínú ẹnì kan, á gba àwọn ibi tí kò lómi kọjá láti wá ibi ìsinmi, tí kò bá sì rí ìkankan, á sọ pé, ‘Màá pa dà sí ilé mi tí mo ti kúrò.’+ 25  Tó bá sì dé, á rí i pé wọ́n ti gbá ilé náà mọ́, wọ́n sì ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. 26  Á wá lọ mú ẹ̀mí méje míì dání, tí wọ́n burú ju òun fúnra rẹ̀ lọ, lẹ́yìn tí wọ́n bá sì wọlé, wọ́n á máa gbé ibẹ̀. Ipò ẹni yẹn nígbẹ̀yìn á wá burú ju ti tẹ́lẹ̀ lọ.” 27  Bó ṣe ń sọ àwọn nǹkan yìí, obìnrin kan kígbe láàárín èrò, ó sọ fún un pé: “Aláyọ̀ ni ilé ọlẹ̀ tó gbé ọ àti ọmú tí o mu!”+ 28  Àmọ́ ó sọ pé: “Rárá o, kàkà bẹ́ẹ̀, aláyọ̀ ni àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí wọ́n sì ń pa á mọ́!”+ 29  Nígbà tí àwọn èrò ń kóra jọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í sọ pé: “Ìran burúkú ni ìran yìí; ó ń wá àmì, àmọ́ a ò ní fún un ní àmì kankan àfi àmì Jónà.+ 30  Torí bí Jónà+ ṣe di àmì fún àwọn ará Nínéfè, bẹ́ẹ̀ náà ni Ọmọ èèyàn ṣe máa jẹ́ fún ìran yìí. 31  A máa gbé ọbabìnrin gúúsù+ dìde láti ṣèdájọ́ àwọn èèyàn ìran yìí, ó sì máa dá wọn lẹ́bi, torí ó wá láti ìkángun ayé kó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ ọgbọ́n Sólómọ́nì. Àmọ́ ẹ wò ó! ohun kan tó ju Sólómọ́nì lọ wà níbí.+ 32  Àwọn ará Nínéfè máa dìde láti ṣèdájọ́ ìran yìí, wọ́n á sì dá a lẹ́bi, torí pé wọ́n ronú pìwà dà nígbà tí Jónà wàásù fún wọn.+ Àmọ́ ẹ wò ó! ohun kan tó ju Jónà lọ wà níbí. 33  Tí ẹnì kan bá tan fìtílà, kò ní gbé e síbi tó fara pa mọ́ tàbí sábẹ́ apẹ̀rẹ̀,* àmọ́ orí ọ̀pá fìtílà ló máa gbé e sí,+ kí àwọn tó bá wọlé lè rí ìmọ́lẹ̀. 34  Ojú rẹ ni fìtílà ara. Tí ojú rẹ bá mú ọ̀nà kan,* gbogbo ara rẹ náà máa mọ́lẹ̀ yòò;* àmọ́ tó bá ń ṣe ìlara,* ara rẹ náà máa ṣókùnkùn.+ 35  Torí náà, wà lójúfò, kí ìmọ́lẹ̀ tó wà nínú rẹ má bàa jẹ́ òkùnkùn. 36  Nítorí náà, tí gbogbo ara rẹ bá mọ́lẹ̀ yòò, tí kò sí apá kankan níbẹ̀ tó ṣókùnkùn, gbogbo rẹ̀ máa mọ́lẹ̀ yòò bí ìgbà tí fìtílà bá fi ìtànṣán rẹ̀ tan ìmọ́lẹ̀ fún ọ.” 37  Nígbà tó sọ èyí, Farisí kan ní kó wá bá òun jẹun. Ó wá wọlé lọ, ó sì jókòó* sídìí tábìlì. 38  Àmọ́ ó ya Farisí náà lẹ́nu nígbà tó rí i pé kò kọ́kọ́ wẹ ọwọ́* kó tó jẹun.+ 39  Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún un pé: “Ẹ̀yin Farisí, ẹ̀ ń fọ ẹ̀yìn ife àti abọ́ mọ́, àmọ́ wọ̀bìà àti ìwà burúkú kún inú yín.+ 40  Ẹ̀yin aláìlóye! Ṣebí ẹni tó ṣe ẹ̀yìn náà ló ṣe inú, àbí òun kọ́? 41  Àwọn ohun tó wá láti inú ni kí ẹ máa fi ṣe ìtọrẹ àánú,* ẹ wò ó! gbogbo nǹkan nípa yín máa mọ́. 42  Àmọ́ ẹ gbé ẹ̀yin Farisí, torí pé ẹ̀ ń san ìdá mẹ́wàá ewéko míńtì, ewéko rúè àti gbogbo ewébẹ̀* míì,+ àmọ́ ẹ ò ka ìdájọ́ òdodo àti ìfẹ́ Ọlọ́run sí! Àwọn nǹkan yìí ló pọn dandan kí ẹ ṣe, àmọ́ kò yẹ kí ẹ ṣàìka àwọn nǹkan yòókù yẹn sí.+ 43  Ẹ gbé, ẹ̀yin Farisí, torí ẹ fẹ́ràn ìjókòó iwájú* nínú sínágọ́gù, ẹ sì fẹ́ràn kí wọ́n máa kí yín níbi ọjà!+ 44  Ẹ gbé, torí pé ẹ dà bí àwọn ibojì* tí kò ṣeé rí kedere,*+ tí àwọn èèyàn ń rìn lórí rẹ̀ láìmọ̀!” 45  Ọ̀kan nínú àwọn tó mọ Òfin dunjú dá a lóhùn pé: “Olùkọ́, bí o ṣe ń sọ àwọn nǹkan yìí, ò ń sọ̀rọ̀ sí àwa náà.” 46  Ó wá sọ pé: “Kódà, ẹ̀yin tí ẹ mọ Òfin dunjú gbé, torí pé ẹ̀ ń di àwọn ẹrù tó ṣòroó gbé ru àwọn èèyàn, àmọ́ ẹ̀yin fúnra yín ò fi ọ̀kan nínú àwọn ìka yín kan àwọn ẹrù náà!+ 47  “Ẹ gbé, torí pé ẹ̀ ń kọ́ ibojì* àwọn wòlíì, àmọ́ àwọn baba ńlá yín ló pa wọ́n!+ 48  Ó dájú pé ẹ jẹ́ ẹlẹ́rìí àwọn ohun táwọn baba ńlá yín ṣe, síbẹ̀, ẹ fọwọ́ sí i, torí pé wọ́n pa àwọn wòlíì,+ àmọ́ ẹ̀ ń kọ́ ibojì wọn. 49  Ìdí nìyẹn tí ọgbọ́n Ọlọ́run náà fi sọ pé: ‘Màá rán àwọn wòlíì àti àwọn àpọ́sítélì sí wọn, wọ́n máa pa àwọn kan, wọ́n sì máa ṣe inúnibíni sí àwọn kan lára wọn, 50  ká lè di ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn wòlíì tí wọ́n ta sílẹ̀ látìgbà ìpìlẹ̀ ayé ru* ìran yìí,+ 51  látorí ẹ̀jẹ̀ Ébẹ́lì+ títí dórí ẹ̀jẹ̀ Sekaráyà, tí wọ́n pa láàárín pẹpẹ àti ilé.’*+ Àní, mò ń sọ fún yín, a máa di ẹ̀bi rẹ̀ ru* ìran yìí. 52  “Ẹ gbé, ẹ̀yin tí ẹ mọ Òfin dunjú, torí ẹ mú kọ́kọ́rọ́ ìmọ̀ lọ. Ẹ̀yin fúnra yín ò wọlé, ẹ sì ń dí àwọn tó ń wọlé lọ́wọ́!”+ 53  Torí náà, nígbà tó kúrò níbẹ̀, àwọn akọ̀wé òfin àti àwọn Farisí bẹ̀rẹ̀ sí í yọ ọ́ lẹ́nu gidigidi, wọ́n sì ń da ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbéèrè míì bò ó, 54  wọ́n ń ṣọ́ ọ, kí wọ́n lè fi ohun tó bá sọ mú un.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “kí a bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ; kí a ka orúkọ rẹ sí mímọ́.”
Orúkọ tí wọ́n ń pe Sátánì.
Tàbí “apẹ̀rẹ̀ ìdíwọ̀n.”
Tàbí “ríran kedere.”
Tàbí “kún fún ìmọ́lẹ̀.”
Ní Grk., “burú.”
Tàbí “rọ̀gbọ̀kú.”
Ìyẹn, láti wẹ ara rẹ̀ mọ́, bí àṣà ìwẹ̀mọ́.
Tàbí “ìtọrẹ fún àwọn aláìní.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “ewéko.”
Tàbí “tó dáa jù.”
Tàbí “àwọn ibojì tí wọn ò sàmì sí.”
Tàbí “àwọn ibojì ìrántí.”
Tàbí “ibojì ìrántí.”
Tàbí “ká lè béèrè ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn wòlíì tí wọ́n ta sílẹ̀ látìgbà ìpìlẹ̀ ayé lọ́wọ́.”
Tàbí “tẹ́ńpìlì.”
Tàbí “a máa béèrè rẹ̀ lọ́wọ́.”