Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìwé Jeremáyà

Orí

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Yìí

  • 1

    • Ọlọ́run yan Jeremáyà láti jẹ́ wòlíì (1-10)

    • Ìran nípa igi álímọ́ńdì (11, 12)

    • Ìran nípa ìkòkò ìsebẹ̀ (13-16)

    • Ọlọ́run fún Jeremáyà lágbára kó lè jẹ́ iṣẹ́ tó rán an (17-19)

  • 2

    • Ísírẹ́lì fi Jèhófà sílẹ̀ láti lọ jọ́sìn àwọn ọlọ́run míì (1-37)

      • Ísírẹ́lì dà bí àjàrà ilẹ̀ òkèèrè (21)

      • Ẹ̀jẹ̀ ta sí i láṣọ (34)

  • 3

    • Bí ìpẹ̀yìndà Ísírẹ́lì ṣe burú tó (1-5)

    • Ísírẹ́lì àti Júdà jẹ̀bi àgbèrè (6-11)

    • Ọlọ́run ní kí wọ́n ronú pìwà dà (12-25)

  • 4

    • Ìrònúpìwàdà ń mú ìbùkún wá (1-4)

    • Àjálù yóò wá láti àríwá (5-18)

    • Àjálù tó ń bọ̀ kó ẹ̀dùn ọkàn bá Jeremáyà (19-31)

  • 5

    • Àwọn èèyàn náà kò gba ìbáwí Jèhófà (1-13)

    • Ìparun ń bọ̀, àmọ́ kì í ṣe ìparun pátápátá (14-19)

    • Jèhófà pe àwọn èèyàn náà wá jíhìn (20-31)

  • 6

    • Ọ̀tá máa tó dó ti Jerúsálẹ́mù (1-9)

    • Ìbínú Jèhófà lórí Jerúsálẹ́mù (10-21)

      • Wọ́n ń sọ pé “Àlàáfíà!” nígbà tí kò sí àlàáfíà (14)

    • Ọ̀tá ya wọ ilẹ̀ náà láti àríwá (22-26)

    • Jeremáyà máa di ẹni tó ń yọ́ wúrà àti fàdákà mọ́ (27-30)

  • 7

    • Ìgbẹ́kẹ̀lé asán nípa tẹ́ńpìlì Jèhófà (1-11)

    • Tẹ́ńpìlì náà yóò dà bíi Ṣílò (12-15)

    • Ọlọ́run kọ ìjọsìn wọn (16-34)

      • Wọ́n jọ́sìn “Ọbabìnrin Ọ̀run” (18)

      • Wọ́n ń fi ọmọ rúbọ ní Hínómù (31)

  • 8

    • Àwọn èèyàn náà ń ṣe ohun tí ọ̀pọ̀ èèyàn ń ṣe (1-7)

    • Ǹjẹ́ ọgbọ́n lè wà láìsí ọ̀rọ̀ Jèhófà? (8-17)

    • Jeremáyà kédàárò lórí ìṣubú Júdà (18-22)

      • “Ṣé kò sí básámù ní Gílíádì ni?” (22)

  • 9

    • Ìbànújẹ́ Jeremáyà pọ̀ gan-an (1-3a)

    • Jèhófà pe Júdà wá jíhìn (3b-16)

    • Ìdárò lórí Júdà (17-22)

    • Máa yangàn torí pé o mọ Jèhófà (23-26)

  • 10

    • Àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè àti Ọlọ́run alààyè (1-16)

    • Ìparun àti ìgbèkùn ń bọ̀ lọ́nà (17, 18)

    • Inú Jeremáyà bà jẹ́ (19-22)

    • Àdúrà tí wòlíì náà gbà (23-25)

      • Èèyàn kò lè darí ìṣísẹ̀ ara rẹ̀ (23)

  • 11

    • Júdà da májẹ̀mú Ọlọ́run (1-17)

      • Àwọn ọlọ́run pọ̀ bí ìlú ṣe pọ̀ (13)

    • Jeremáyà dà bí ọ̀dọ́ àgùntàn tí wọ́n fẹ́ lọ pa (18-20)

    • Àtakò tí àwọn ará ìlú Jeremáyà ṣe (21-23)

  • 12

    • Jeremáyà mú ẹjọ́ rẹ̀ wá (1-4)

    • Ohun tí Jèhófà sọ (5-17)

  • 13

    • Àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀ tó bà jẹ́ (1-11)

    • Ọlọ́run máa fọ́ àwọn ìṣà wáìnì (12-14)

    • Júdà alágídí máa lọ sí ìgbèkùn (15-27)

      • “Ǹjẹ́ ọmọ Kúṣì lè yí àwọ̀ rẹ̀ pa dà?” (23)

  • 14

    • Ọ̀dá, ìyàn àti idà (1-12)

    • Ọlọ́run dá àwọn wòlíì èké lẹ́bi (13-18)

    • Jeremáyà sọ ẹ̀ṣẹ̀ tí àwọn èèyàn náà dá (19-22)

  • 15

    • Jèhófà kò ní yí ìdájọ́ rẹ̀ pa dà (1-9)

    • Jeremáyà mú ẹjọ́ rẹ̀ wá (10)

    • Ohun tí Jèhófà sọ (11-14)

    • Àdúrà Jeremáyà (15-18)

      • Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó jẹ mú kí inú rẹ̀ dùn (16)

    • Jèhófà fún Jeremáyà lágbára (19-21)

  • 16

    • Jeremáyà kò gbọ́dọ̀ gbéyàwó tàbí kó ṣọ̀fọ̀, kò sì gbọ́dọ̀ jẹ àsè (1-9)

    • Ìjìyà, lẹ́yìn náà ìpadàbọ̀sípò (10-21)

  • 17

    • Júdà ti jingíri sínú ẹ̀ṣẹ̀ (1-4)

    • Ìbùkún tó wà nínú gbígbẹ́kẹ̀lé Jèhófà (5-8)

    • Ọkàn tó ń tanni jẹ (9-11)

    • Jèhófà jẹ́ ìrètí Ísírẹ́lì (12, 13)

    • Àdúrà Jeremáyà (14-18)

    • Jẹ́ kí Sábáàtì wà ní mímọ́ (19-27)

  • 18

    • Amọ̀ tó wà lọ́wọ́ amọ̀kòkò (1-12)

    • Jèhófà kẹ̀yìn sí Ísírẹ́lì (13-17)

    • Wọ́n gbìmọ̀ ibi sí Jeremáyà; ó ké pe Ọlọ́run (18-23)

  • 19

    • Ọlọ́run sọ pé kí Jeremáyà fọ́ ṣágo amọ̀ (1-15)

      • Wọ́n fi ọmọ rúbọ sí Báálì (5)

  • 20

    • Páṣúrì lu Jeremáyà (1-6)

    • Jeremáyà ò lè dákẹ́ ìwàásù (7-13)

      • Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run dà bí iná tó ń jó (9)

      • Jèhófà dà bíi jagunjagun tó ń bani lẹ́rù (11)

    • Jeremáyà mú ẹjọ́ rẹ̀ wá (14-18)

  • 21

    • Jèhófà kọ ẹ̀bẹ̀ Sedekáyà (1-7)

    • Àwọn èèyàn yóò yan ikú tàbí ìyè (8-14)

  • 22

    • Ọ̀rọ̀ ìdájọ́ sí àwọn ọba búburú (1-30)

      • Nípa Ṣálúmù (10-12)

      • Nípa Jèhóákímù (13-23)

      • Nípa Konáyà (24-30)

  • 23

    • Àwọn olùṣọ́ àgùntàn rere àti búburú (1-4)

    • Ààbò lábẹ́ “èéhù kan tí ó jẹ́ olódodo” (5-8)

    • Ọlọ́run dá àwọn wòlíì èké lẹ́bi (9-32)

    • “Ẹrù tó wúwo” látọ̀dọ̀ Jèhófà (33-40)

  • 24

    • Àwọn ọ̀pọ̀tọ́ tó dára àtèyí tó ti bà jẹ́ (1-10)

  • 25

    • Ìdájọ́ Jèhófà lórí àwọn orílẹ̀-èdè (1-38)

      • Àwọn orílẹ̀-èdè máa fi 70 ọdún sin Bábílónì (11)

      • Ife wáìnì ìbínú Ọlọ́run (15)

      • Àjálù láti orílẹ̀-èdè dé orílẹ̀-èdè (32)

      • Àwọn tí Jèhófà pa (33)

  • 26

    • Wọ́n fi ikú halẹ̀ mọ́ Jeremáyà (1-15)

    • Wọ́n dá Jeremáyà sí (16-19)

      • Wọ́n fa ọ̀rọ̀ yọ látinú àsọtẹ́lẹ̀ Míkà (18)

    • Wòlíì Úríjà (20-24)

  • 27

    • Àjàgà Bábílónì (1-11)

    • Ọlọ́run ní kí Sedekáyà fi ara rẹ̀ sábẹ́ Bábílónì (12-22)

  • 28

    • Jeremáyà àti Hananáyà tó jẹ́ wòlíì èké (1-17)

  • 29

    • Lẹ́tà tí Jeremáyà kọ sí àwọn tó wà ní ìgbèkùn ní Bábílónì (1-23)

      • Ísírẹ́lì yóò pa dà lẹ́yìn 70 ọdún (10)

    • Iṣẹ́ tí wọ́n rán sí Ṣemáyà (24-32)

  • 30

    • Ìlérí ìpadàbọ̀sípò àti ìmúláradá (1-24)

  • 31

    • Àwọn tó ṣẹ́ kù ní Ísírẹ́lì á tún pa dà máa gbé ilẹ̀ wọn (1-30)

      • Réṣẹ́lì ń sunkún nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ (15)

    • Májẹ̀mú tuntun (31-40)

  • 32

    • Jeremáyà ra ilẹ̀ (1-15)

    • Àdúrà Jeremáyà (16-25)

    • Ohun tí Jèhófà sọ (26-44)

  • 33

    • Ìlérí ìpadàbọ̀sípò (1-13)

    • Ààbò lábẹ́ “èéhù òdodo” (14-16)

    • Májẹ̀mú tí Ọlọ́run bá Dáfídì àti àwọn àlùfáà dá (17-26)

      • Májẹ̀mú nípa ọ̀sán àti òru (20)

  • 34

    • Ọ̀rọ̀ ìdájọ́ sí Sedekáyà (1-7)

    • Wọ́n da májẹ̀mú tí wọ́n dá pé wọ́n á dá àwọn ẹrú sílẹ̀ (8-22)

  • 35

    • Àwọn ọmọ Rékábù jẹ́ onígbọràn tó ṣeé fara wé (1-19)

  • 36

    • Jeremáyà ń sọ ohun tí wọ́n ń kọ sínú àkájọ ìwé (1-7)

    • Bárúkù ka ọ̀rọ̀ inú àkájọ ìwé sókè (8-19)

    • Jèhóákímù dáná sun àkájọ ìwé náà (20-26)

    • A tún ọ̀rọ̀ náà kọ sínú àkájọ ìwé tuntun (27-32)

  • 37

    • Àwọn ará Kálídíà ṣígun lọ fúngbà díẹ̀ (1-10)

    • Wọ́n fi Jeremáyà sẹ́wọ̀n (11-16)

    • Sedekáyà pàdé Jeremáyà (17-21)

      • Wọ́n ń fún Jeremáyà ní búrẹ́dì (21)

  • 38

    • Wọ́n ju Jeremáyà sínú kòtò omi (1-6)

    • Ebedi-mélékì gba Jeremáyà sílẹ̀ (7-13)

    • Jeremáyà rọ Sedekáyà pé kó juwọ́ sílẹ̀ (14-28)

  • 39

    • Ìṣubú Jerúsálẹ́mù (1-10)

      • Sedekáyà fẹsẹ̀ fẹ, ṣùgbọ́n wọ́n gbá a mú (4-7)

    • Wọ́n máa dáàbò bo Jeremáyà (11-14)

    • Ọlọ́run máa dá ẹ̀mí Ebedi-mélékì sí (15-18)

  • 40

    • Nebusarádánì jẹ́ kí Jeremáyà lọ ní òmìnira (1-6)

    • A yan Gẹdaláyà ṣe olórí ilẹ̀ náà (7-12)

    • Wọ́n dìtẹ̀ Gẹdaláyà (13-16)

  • 41

    • Íṣímáẹ́lì pa Gẹdaláyà (1-10)

    • Íṣímáẹ́lì fẹsẹ̀ fẹ bó ṣe rí Jóhánánì (11-18)

  • 42

    • Àwọn èèyàn ní kí Jeremáyà gbàdúrà fún ìtọ́sọ́nà (1-6)

    • Jèhófà fèsì pé: “Ẹ má lọ sí Íjíbítì” (7-22)

  • 43

    • Àwọn èèyàn ṣàìgbọràn, wọ́n lọ sí Íjíbítì (1-7)

    • Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ fún Jeremáyà ní Íjíbítì (8-13)

  • 44

    • Àsọtẹ́lẹ̀ nípa àjálù fún àwọn Júù tó wà ní Íjíbítì (1-14)

    • Àwọn èèyàn kò gba ìkìlọ̀ Ọlọ́run (15-30)

      • Wọ́n jọ́sìn “Ọbabìnrin Ọ̀run” (17-19)

  • 45

    • Iṣẹ́ tí Jèhófà rán sí Bárúkù (1-5)

  • 46

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Íjíbítì (1-26)

      • Nebukadinésárì yóò ṣẹ́gun Íjíbítì (13, 26)

    • Ìlérí tí Ọlọ́run ṣe fún Ísírẹ́lì (27, 28)

  • 47

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí àwọn Filísínì (1-7)

  • 48

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Móábù (1-47)

  • 49

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí àwọn ọmọ Ámónì (1-6)

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Édómù (7-22)

      • Édómù kò ní jẹ́ orílẹ̀-èdè mọ́ (17, 18)

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Damásíkù (23-27)

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Kédárì àti Hásórì (28-33)

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Élámù (34-39)

  • 50

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Bábílónì (1-46)

      • Ẹ sá kúrò nínú Bábílónì (8)

      • A ó mú Ísírẹ́lì pa dà wá (17-19)

      • A ó mú kí odò Bábílónì gbẹ (38)

      • Ẹnikẹ́ni kò ní gbé Bábílónì mọ́ (39, 40)

  • 51

    • Àsọtẹ́lẹ̀ lórí Bábílónì (1-64)

      • Bábílónì máa ṣubú lójijì sọ́wọ́ àwọn ará Mídíà (8-12)

      • Ó ju ìwé sínú odò Yúfírétì (59-64)

  • 52

    • Sedekáyà ṣọ̀tẹ̀ sí Bábílónì (1-3)

    • Nebukadinésárì dó ti Jerúsálẹ́mù (4-11)

    • Ìparun Jerúsálẹ́mù àti tẹ́ńpìlì rẹ̀ (12-23)

    • Wọ́n kó àwọn èèyàn lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì (24-30)

    • Wọ́n dá Jèhóákínì sílẹ̀ lẹ́wọ̀n (31-34)