Jóòbù 2:1-13

  • Sátánì tún fẹ̀sùn kan Jóòbù (1-5)

  • Ọlọ́run fàyè gba Sátánì pé kó kọlu ara Jóòbù (6-8)

  • Ìyàwó Jóòbù sọ pé: “Sọ̀rọ̀ òdì sí Ọlọ́run, kí o sì kú!” (9, 10)

  • Àwọn ọ̀rẹ́ Jóòbù mẹ́ta dé (11-13)

2  Lẹ́yìn náà, nígbà tó di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Ọlọ́run tòótọ́*+ ń wọlé láti dúró níwájú Jèhófà,+ Sátánì náà wọlé sáàárín wọn kó lè dúró níwájú Jèhófà.+  Jèhófà bi Sátánì pé: “Ibo lo ti ń bọ̀?” Sátánì dá Jèhófà lóhùn pé: “Látinú ayé, mo lọ káàkiri, mo sì rìn káàkiri nínú rẹ̀.”+  Jèhófà sì bi Sátánì pé: “Ṣé o ti kíyè sí* Jóòbù ìránṣẹ́ mi? Kò sí ẹni tó dà bí rẹ̀ ní ayé. Olódodo àti olóòótọ́* èèyàn+ ni, ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ó sì kórìíra ohun tó burú. Kò fi ìwà títọ́ rẹ̀ sílẹ̀ rárá,+ bó tiẹ̀ jẹ́ pé o fẹ́ sún mi+ láti pa á run* láìnídìí.”  Àmọ́, Sátánì dá Jèhófà lóhùn pé: “Awọ dípò awọ. Gbogbo ohun tí èèyàn bá ní ló máa fi dípò ẹ̀mí* rẹ̀.  Àmọ́, kí nǹkan lè yí pa dà, na ọwọ́ rẹ, kí o sì kọ lu egungun àti ara rẹ̀, ó dájú pé ó máa bú ọ níṣojú rẹ gan-an.”+  Jèhófà wá sọ fún Sátánì pé: “Wò ó! Ó wà ní ọwọ́ rẹ!* Àmọ́, o ò gbọ́dọ̀ gba ẹ̀mí* rẹ̀!”  Ni Sátánì bá jáde kúrò níwájú* Jèhófà, ó sì fi eéwo tó ń roni lára*+ kọ lu Jóòbù láti àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀.  Jóòbù wá mú àfọ́kù ìkòkò, ó sì fi ń họ ara rẹ̀, ó wá jókòó sínú eérú.+  Níkẹyìn, ìyàwó rẹ̀ sọ fún un pé: “Ṣé pé o ò tíì fi ìwà títọ́ rẹ sílẹ̀? Sọ̀rọ̀ òdì sí Ọlọ́run, kí o sì kú!” 10  Àmọ́ Jóòbù sọ fún un pé: “Ò ń sọ̀rọ̀ bí ọ̀kan lára àwọn obìnrin tí kò nírònú. Tí a bá gba ohun rere lọ́wọ́ Ọlọ́run tòótọ́, ṣé kò yẹ ká tún gba ohun búburú?”+ Nínú gbogbo ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí, Jóòbù kò fi ẹnu rẹ̀ dẹ́ṣẹ̀.+ 11  Àwọn ọ̀rẹ́* Jóòbù mẹ́ta gbọ́ nípa gbogbo àjálù tó dé bá a, kálukú sì wá láti ibi tó ń gbé, Élífásì+ ará Témánì, Bílídádì+ ọmọ Ṣúáhì+ àti Sófárì+ ọmọ Náámà. Wọ́n ṣàdéhùn láti pàdé, kí wọ́n lè lọ bá Jóòbù kẹ́dùn, kí wọ́n sì tù ú nínú. 12  Nígbà tí wọ́n rí i lọ́ọ̀ọ́kán, wọn ò dá a mọ̀. Ni wọ́n bá bú sẹ́kún, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì da iyẹ̀pẹ̀ sínú afẹ́fẹ́ àti sórí ara wọn.+ 13  Wọ́n sì jókòó sílẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀ fún ọ̀sán méje àti òru méje. Ẹnì kankan ò bá a sọ̀rọ̀, torí wọ́n rí i pé ìrora rẹ̀ pọ̀ gan-an.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Àkànlò èdè Hébérù tó ń tọ́ka sí àwọn áńgẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ọmọ Ọlọ́run.
Ní Héb., “fi ọkàn rẹ sí.”
Tàbí “Aláìlẹ́bi àti adúróṣinṣin.”
Ní Héb., “gbé e mì.”
Tàbí “ọkàn rẹ̀.”
Tàbí “ní ìkáwọ́ rẹ.”
Tàbí “ọkàn.”
Ní Héb., “ní ojú.”
Tàbí “àwọn ọgbẹ́ tó le gan-an.”
Tàbí “ojúlùmọ̀.”