Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ìwé Ẹ́kísódù

Orí

Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Yìí

  • 1

    • Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń pọ̀ sí i ní Íjíbítì (1-7)

    • Fáráò ń fìyà jẹ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì (8-14)

    • Àwọn agbẹ̀bí tó bẹ̀rù Ọlọ́run dá ẹ̀mí sí (15-22)

  • 2

    • Wọ́n bí Mósè (1-4)

    • Ọmọbìnrin Fáráò fi Mósè ṣe ọmọ rẹ̀ (5-10)

    • Mósè sá lọ sí Mídíánì, ó sì fẹ́ Sípórà (11-22)

    • Ọlọ́run gbọ́ bí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ń kérora (23-25)

  • 3

    • Mósè àti igi ẹlẹ́gùn-ún tó ń jó (1-12)

    • Jèhófà sọ ìtúmọ̀ orúkọ Rẹ̀ (13-15)

    • Jèhófà fún Mósè ní ìtọ́ni (16-22)

  • 4

    • Iṣẹ́ àmì mẹ́ta tí Mósè máa ṣe (1-9)

    • Mósè ní òun ò kúnjú ìwọ̀n (10-17)

    • Mósè pa dà sí Íjíbítì (18-26)

    • Mósè àti Áárónì tún jọ pàdé (27-31)

  • 5

    • Mósè àti Áárónì lọ bá Fáráò (1-5)

    • Wọ́n túbọ̀ fìyà jẹ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì (6-18)

    • Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì dá Mósè àti Áárónì lẹ́bi (19-23)

  • 6

    • Ọlọ́run tún ṣèlérí òmìnira ((1-13)

      • Wọn ò mọ orúkọ Jèhófà délẹ̀délẹ̀ (2, 3)

    • Ìlà ìdílé Mósè àti Áárónì (14-27)

    • Mósè tún máa lọ sọ́dọ̀ Fáráò (28-30)

  • 7

    • Jèhófà fún Mósè lókun (1-7)

    • Ọ̀pá Áárónì di ejò ńlá (8-13)

    • Ìyọnu 1: omi di ẹ̀jẹ̀ (14-25)

  • 8

    • Ìyọnu 2: àkèré (1-15)

    • Ìyọnu 3: kòkòrò abìyẹ́ tó ń mùjẹ̀ (16-19)

    • Ìyọnu 4: eṣinṣin mùjẹ̀mùjẹ̀ (20-32)

      • Ìyọnu ò dé ilẹ̀ Góṣénì 22, 23)

  • 9

    • Ìyọnu 5: àwọn ẹran ọ̀sìn kú (1-7)

    • Ìyọnu 6: eéwo yọ sára èèyàn àti ẹranko (8-12)

    • Ìyọnu 7: òjò yìnyín (13-35)

      • Fáráò yóò rí agbára Ọlọ́run (16)

      • Wọ́n á mọ orúkọ Jèhófà (16)

  • 10

    • Ìyọnu 8: eéṣú (1-20)

    • Ìyọnu 9: òkùnkùn (21-29)

  • 11

    • Ó kéde ìyọnu kẹwàá (1-10)

      • Kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì béèrè ẹ̀bùn (2)

  • 12

    • Ó fi Ìrékọjá lọ́lẹ̀ (1-28)

      • Wọ́n máa wọ́n ẹ̀jẹ̀ sára àwọn òpó ilẹ̀kùn (7)

    • Ìyọnu 10: Ó pa àkọ́bí (29-32)

    • Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kúrò ní ilẹ̀ náà (33-42)

    • Ìtọ́ni fún àwọn tó fẹ́ ṣe Ìrékọjá (43-51)

  • 13

    • Ti Jèhófà ni gbogbo àkọ́bí tó jẹ́ akọ (1, 2)

    • Àjọyọ̀ Búrẹ́dì Aláìwú (3-10)

    • Kí wọ́n ya gbogbo àkọ́bí tó jẹ́ akọ sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run (11-16)

    • Ọlọ́run darí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gba ọ̀nà Òkun Pupa (17-20)

    • Ọwọ̀n ìkùukùu àti ọwọ̀n iná (21, 22)

  • 14

    • Ísírẹ́lì dé òkun (1-4)

    • Fáráò ń lépa àwọn ọmọ Ísírẹ́lì (5-14)

    • Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọdá Òkun Pupa (15-25)

    • Àwọn ará Íjíbítì rì sínú òkun (26-28)

    • Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà (29-31)

  • 15

    • Mósè àti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kọrin ìṣẹ́gun (1-19)

    • Míríámù fi orin dáhùn pa dà (20, 21)

    • Omi tó korò wá dùn (22-27)

  • 16

    • Àwọn èèyàn ń ráhùn torí oúnjẹ (1-3)

    • Jèhófà gbọ́ ìráhùn wọn (4-12)

    • Ó fún wọn ní ẹyẹ àparò àti mánà (13-21)

    • Kò sí mánà lọ́jọ́ Sábáàtì (22-30)

    • Wọ́n tọ́jú mánà fún ìrántí (31-36)

  • 17

    • Wọ́n ráhùn pé wọn ò rí omi mu ní Hórébù (1-4)

    • Omi jáde látinú àpáta (5-7)

    • Àwọn ọmọ Ámálékì gbógun ja Ísírẹ́lì, àmọ́ wọn ò borí (8-16)

  • 18

    • Jẹ́tírò àti Sípórà dé (1-12)

    • Jẹ́tírò ní kó yan àwọn adájọ́ (13-27)

  • 19

    • Ní Òkè Sínáì (1-25)

      • Ísírẹ́lì yóò di ìjọba àwọn àlùfáà (5, 6)

      • Ó sọ àwọn èèyàn di mímọ́ láti pàdé Ọlọ́run (14, 15)

  • 20

    • Òfin Mẹ́wàá (1-17)

    • Ohun tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì rí dẹ́rù bà wọ́n (18-21)

    • Ìtọ́ni nípa ìjọsìn (22-26)

  • 21

    • Ìdájọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa tẹ̀ lé (1-36)

      • Tí wọ́n bá ra Hébérù ní ẹrú (2-11)

      • Tí ẹnì kan bá hùwà ipá sí ẹnì kejì (12-27)

      • Nípa àwọn ẹranko (28-36)

  • 22

    • Ìdájọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa tẹ̀ lé (1-31)

      • Tí ẹnì kan bá jalè (1-4)

      • Tí ẹnì kan bá ba irè oko ẹlòmíì jẹ́ (5, 6)

      • Nípa àsanfidípò àti ohun ìní (7-15)

      • Nípa fífa ojú wúńdíá mọ́ra (16, 17)

      • Nípa ìjọsìn àti ohun tó tọ́ láwùjọ (18-31)

  • 23

    • Ìdájọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa tẹ̀ lé (1-19)

      • Nípa ìṣòtítọ́ àti ìwà tó tọ́ (1-9)

      • Nípa sábáàtì àti àwọn àjọyọ̀ (10-19)

    • Áńgẹ́lì yóò máa darí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì (20-26)

    • Gbígba ilẹ̀ àti ààlà (27-33)

  • 24

    • Àwọn èèyàn gbà láti pa májẹ̀mú mọ́ (1-11)

    • Mósè lọ sórí Òkè Sínáì (12-18)

  • 25

    • Ọrẹ àgọ́ ìjọsìn (1-9)

    • Àpótí (10-22)

    • Tábìlì (23-30)

    • Ọ̀pá fìtílà (31-40)

  • 26

    • Àgọ́ ìjọsìn (1-37)

      • Àwọn aṣọ àgọ́ (1-14)

      • Àwọn férémù àti àwọn ìtẹ́lẹ̀ oníhò (15-30)

      • Aṣọ ìdábùú àti aṣọ tí wọ́n máa ta sí ẹnu ọ̀nà (31-37)

  • 27

    • Pẹpẹ ẹbọ sísun (1-8)

    • Àgbàlá (9-19)

    • Òróró ọ̀pá fìtílà (20, 21)

  • 28

    • Àwọn aṣọ àlùfáà (1-5)

    • Éfódì (6-14)

    • Aṣọ ìgbàyà (15-30)

      • Úrímù àti Túmímù (30)

    • Aṣọ àwọ̀lékè tí kò lápá (31-35)

    • Láwàní àti àwo dídán (36-39)

    • Àwọn aṣọ míì tó jẹ́ ti àwọn àlùfáà (40-43)

  • 29

    • Fífi iṣẹ́ lé àwọn àlùfáà lọ́wọ́ (1-37)

    • Ọrẹ ojoojúmọ́ (38-46)

  • 30

    • Pẹpẹ tùràrí (1-10)

    • Ìkànìyàn àti owó ètùtù (11-16)

    • Bàsíà bàbà láti máa fi wẹ̀ (17-21)

    • Àkànṣe òróró àfiyanni (22-33)

    • Àwọn èròjà tùràrí mímọ́ (34-38)

  • 31

    • Ọlọ́run fi ẹ̀mí rẹ̀ kún inú àwọn oníṣẹ́ ọnà (1-11)

    • Sábáàtì jẹ́ àmì láàárín Ọlọ́run àti Ísírẹ́lì (12-17)

    • Wàláà òkúta méjì (18)

  • 32

    • Wọ́n jọ́sìn ère ọmọ màlúù (1-35)

      • Mósè gbọ́ orin tó ṣàjèjì (17, 18)

      • Mósè fọ́ àwọn wàláà òfin túútúú (19)

      • Àwọn ọmọ Léfì ò fi Jèhófà sílẹ̀ (26-29)

  • 33

    • Ọlọ́run bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì wí (1-6)

    • Àgọ́ ìpàdé ní ẹ̀yìn ibùdó (7-11)

    • Mósè fẹ́ rí ògo Jèhófà (12-23)

  • 34

    • Ó gbẹ́ àwọn wàláà òkúta míì (1-4)

    • Mósè rí ògo Jèhófà (5-9)

    • Ọlọ́run tún àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà sọ (10-28)

    • Ìtànṣán ń jáde lára awọ ojú Mósè (29-35)

  • 35

    • Àwọn ìtọ́ni Sábáàtì (1-3)

    • Ọrẹ àgọ́ ìjọsìn (4-29)

    • Ọlọ́run fi ẹ̀mí kún inú Bẹ́sálẹ́lì àti Òhólíábù (30-35)

  • 36

    • Ọrẹ náà tó, ó ṣẹ́ kù (1-7)

    • Wọ́n kọ́ àgọ́ ìjọsìn (8-38)

  • 37

    • Ó ṣe Àpótí (1-9)

    • Tábìlì (10-16)

    • Ọ̀pá fìtílà (17-24)

    • Pẹpẹ tùràrí (25-29)

  • 38

    • Pẹpẹ ẹbọ sísun (1-7)

    • Ó fi bàbà ṣe bàsíà (8)

    • Àgbàlá (9-20)

    • Wọ́n ka àwọn ohun èlò àgọ́ ìjọsìn (21-31)

  • 39

    • Wọ́n ṣe àwọn aṣọ àlùfáà (1)

    • Éfódì (2-7)

    • Aṣọ ìgbàyà (8-21)

    • Aṣọ àwọ̀lékè tí kò lápá (22-26)

    • Àwọn aṣọ míì tó jẹ́ ti àwọn àlùfáà (27-29)

    • Àwo wúrà (30, 31)

    • Mósè yẹ iṣẹ́ tí wọ́n ṣe sí àgọ́ ìjọsìn wò (32-43)

  • 40

    • Wọ́n to àgọ́ ìjọsìn (1-33)

    • Ògo Jèhófà kún inú àgọ́ ìjọsìn (34-38)