Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Ẹ̀KỌ́ 4

Ta Ni Jésù Kristi?

Ta Ni Jésù Kristi?

1. Ibo ni Jésù ti wá?

Àwọn ìwà wo ni Jésù ní tó jẹ́ kó ṣeé sún mọ́?—MÁTÍÙ 11:29; MÁÀKÙ 10:13-16.

Jésù yàtọ̀ sí àwa èèyàn torí pé áńgẹ́lì ni, ọ̀run ló sì ń gbé kí wọ́n tó bí i sí ayé. (Jòhánù 8:23) Òun ni Ọlọ́run kọ́kọ́ dá, ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú Ọlọ́run láti dá gbogbo nǹkan tó kù. Òun nìkan ni Jèhófà fúnra rẹ̀ dá, torí náà ó tọ́ bí wọ́n ṣe pe Jésù ní Ọmọ “bíbí kan ṣoṣo” Ọlọ́run. (Jòhánù 1:14) Jésù tún jẹ́ Agbọ̀rọ̀sọ fún Ọlọ́run, ìdí nìyẹn tí a ṣe pè é ní “Ọ̀rọ̀ náà.”​—Ka Òwe 8:22, 23, 30; Kólósè 1:15, 16.

2. Kí nìdí tí Jésù fi wá sáyé?

Bí Ọlọ́run ṣe rán Ọmọ rẹ̀ wá sáyé láti ọ̀run ni pé, ó fi ẹ̀mí ọmọ náà sínú ilé ọlẹ̀ wúńdíá Júù kan tó ń jẹ́ Màríà. Torí náà, Jésù kò ní bàbá tó jẹ́ èèyàn. (Lúùkù 1:30-35) Jésù wá sí ayé (1) kó lè kọ́ wa ní òtítọ́ nípa Ọlọ́run, (2) kó lè fi àpẹẹrẹ bá a ṣe lè máa ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run lélẹ̀ fún wa, kódà nígbà tá a bá wà nínú ìṣòro, àti pé (3) kó lè fi ẹ̀mí rẹ̀ pípé ṣe “ìràpadà” fún wa.​—Ka Mátíù 20:28.

3. Kí nìdí tá a fi nílò ìràpadà?

Ìràpadà ni ohun téèyàn san láti gba ẹnì kan sílẹ̀ lọ́wọ́ ikú. (Ẹ́kísódù 21:29, 30) Ọlọ́run ò fẹ́ kí àwa èèyàn máa darúgbó, ká sì máa kú. Báwo la ṣe mọ̀? A rí i nínú Bíbélì pé Ọlọ́run sọ fún Ádámù, ọkùnrin àkọ́kọ́, pé tí ó bá dá “ẹ̀ṣẹ̀,” ó máa kú. Torí náà, ká ní Ádámù ò dẹ́ṣẹ̀ ni, kò ní kú. (Jẹ́nẹ́sísì 2:16, 17; 5:⁠5) Bí Bíbélì ṣe sọ, ọ̀dọ̀ Ádámù ni ikú gbà “wọ” ayé. Nípa bẹ́ẹ̀, ogún tí Ádámù fún gbogbo ọmọ rẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú tó jẹ́ èrè ẹ̀ṣẹ̀. Nítorí náà, a nílò ìràpadà ká lè bọ́ lọ́wọ́ ikú tá a jogún látọ̀dọ̀ Ádámù.​—Ka Róòmù 5:12; 6:⁠23.

Ta ló lè san ìràpadà tó máa jẹ́ ká bọ́ lọ́wọ́ ikú? Tá a bá kú, ìyà ẹ̀ṣẹ̀ tiwa nìkan la san yẹn. Kò sí èèyàn aláìpé tó lè ra ẹlòmíì pa dà lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀.​—Ka Sáàmù 49:7-9.

4. Kí nìdí tí Jésù fi kú?

Jésù kò dà bí àwa èèyàn, ẹni pípé ni. Kì í ṣe torí ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ ló ṣe kú torí pé kò dá ẹ̀ṣẹ̀ kankan. Kàkà bẹ́ẹ̀, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ẹlòmíì ni Jésù ṣe kú. Ìfẹ́ àrà ọ̀tọ̀ tí Ọlọ́run ní sí àwa èèyàn ló mú kó rán Ọmọ rẹ̀ pé kí ó wá kú nítorí wa. Jésù náà fi hàn pé òun nífẹ̀ẹ́ wa bó ṣe ṣègbọràn sí Baba rẹ̀ tó sì wá kú nítorí wa.​—Ka Jòhánù 3:16; Róòmù 5:18, 19.

Wo Fídíò náà Kí Nìdí Tí Jésù Fi Kú?

5. Kí ni Jésù ń ṣe báyìí?

Nígbà tí Jésù wà láyé, ó mú àwọn aláìsàn lára dá, ó jí òkú dìde, ó sì gba àwọn tó wà nínú ìṣòro sílẹ̀. Nípa bẹ́ẹ̀, ó jẹ́ ká mọ ohun tó máa ṣe lọ́jọ́ iwájú fún gbogbo èèyàn tó bá jẹ́ onígbọràn. (Mátíù 15:30, 31; Jòhánù 5:28) Lẹ́yìn tí Jésù kú, Ọlọ́run jí i dìde, ó sì pa dà di ẹ̀dá ẹ̀mí ní ọ̀run. (1 Pétérù 3:18) Jésù wá wà ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run títí Jèhófà fi fún un ní àṣẹ pé kó máa jọba lórí gbogbo ayé. (Hébérù 10:12, 13) Ní báyìí, Jésù jẹ́ Ọba tó ń ṣàkóso ní ọ̀run, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń kéde ìròyìn ayọ̀ yìí kárí ayé.​—Ka Dáníẹ́lì 7:13, 14; Mátíù 24:14.

Láìpẹ́, Jésù máa lo agbára rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Ọba láti fòpin sí ìyà tó ń jẹ aráyé, yóò sì pa àwọn ẹni ibi run. Gbogbo àwọn tó bá ń ṣègbọràn sí Jésù láti fi hàn pé àwọn ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ máa ní ìyè àìnípẹ̀kun nínú Párádísè orí ilẹ̀ ayé.​—Ka Sáàmù 37:9-11.