Gbígbọ́ Bùkátà
Ìlànà Bíbélì ti ran ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́wọ́ láti dín ìṣòro àtirówó gbọ́ bùkátà kù.
NÍ ÈTÒ TÓ DÁA
ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Àwọn ohun tí òṣìṣẹ́ kára gbèrò láti ṣe máa ń yọrí sí rere, àmọ́ ó dájú pé gbogbo àwọn tó bá ń kánjú yóò di aláìní.”—Òwe 21:5.
OHUN TÓ TÚMỌ̀ SÍ: Ó yẹ kó o sapá gidigidi láti máa tẹ̀ lé ètò ìnáwó tó o bá ṣe. Torí náà, kó o tó bẹ̀rẹ̀ sí í náwó, rí i dájú pé o ṣètò bó o ṣe máa ná an. Máa rántí pé kì í ṣe gbogbo ohun tó o fẹ́ lo lè rà lẹ́ẹ̀kan náà. Torí náà, á dáa kó o fọgbọ́n ná owó ẹ.
OHUN TÓ O LÈ ṢE:
-
Máa ṣọ́wó ná. Kọ gbogbo ohun tó o fẹ́ rà sílẹ̀, kó o sì pín wọn sí ìsọ̀rí-ìsọ̀rí. Lẹ́yìn náà, pín owó tó o fẹ́ ná sí ìsọ̀rí kọ̀ọ̀kan. Tó o bá ná ju iye tó o pín sórí ìsọ̀rí kan lọ, yọ díẹ̀ lára owó tó o pín sórí ìsọ̀rí míì láti fi dí i. Bí àpẹẹrẹ, tó o bá ná ju iye tó o rò lọ sórí epo mọ́tò rẹ, yọ lára owó tó o fẹ́ ná sórí ohun tí kò fi bẹ́ẹ̀ pọn dandan láti fi dí i, bóyá kó o mú lára owó tó o fẹ́ fi ṣe fàájì.
-
Má ṣe jẹ gbèsè. Tó bá ṣeé ṣe, gbìyànjú láti má ṣe yáwó lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni. Ńṣe ni kó o sapá láti tọ́jú owó pa mọ́ fúnra ẹ títí tó fi máa pé iye tó o fẹ́ fi ra ohun tó o nílò. Tó o bá gbàwìn ọjà, tètè wá bó o ṣe máa sanwó ọjà náà, tó bá sì jẹ́ pé ńṣe lo yáwó, tètè san owó náà pa dà kí èlé tó bẹ̀rẹ̀ sí í gorí ẹ̀. Àmọ́ tó bá jẹ́ pé àkókò tó o dá ti kọjá, ṣe ìwé fún ẹni tó o jẹ ní gbèsè láti sọ bí wàá ṣe máa san owó náà, kó o sì rí i pé o mú àdéhùn rẹ ṣẹ.
Ìwádìí kan sọ pé àwọn tó máa ń fi káàdì rajà àwìn máa ń náwó púpọ̀ tí wọ́n bá ń ràjà. Torí náà, o ní láti máa kó ara ẹ níjàánu gan-an tó o bá nírú káàdì bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́.
ṢỌ́RA FÁWỌN ÀṢÀ TÓ LÈ KÓ BÁ Ẹ
ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Ọ̀lẹ kì í túlẹ̀ nígbà òtútù, tó bá dìgbà ìkórè, á máa tọrọ torí pé kò ní nǹkan kan.”—Òwe 20:4.
OHUN TÓ TÚMỌ̀ SÍ: Ìṣẹ́ ló máa ń gbẹ̀yìn ọ̀lẹ. Torí náà, máa ṣiṣẹ́ kára, kó o sì máa ṣọwó ná kó o lè lówó tí wàá ná lẹ́yìnwá ọ̀la.
OHUN TÓ O LÈ ṢE:
-
Ṣiṣẹ́ kára. Tó o bá gbájú mọ́ṣẹ́, tó o sì jẹ́ ẹni tó ṣeé fọkàn tán, ọgá ẹ á fẹ́ràn ẹ, kò sì ní fẹ́ fi ẹ́ sílẹ̀.
-
Jẹ́ olóòótọ́. Má ṣe ja ọ̀gá ẹ lólè. Ìwà àìṣòótọ́ lè bà ẹ́ lórúkọ jẹ́, kó sì mú kó ṣòro fún ẹ láti ríṣẹ́ míì.
-
Má ṣe jẹ́ olójúkòkòrò. Tó o bá ń lépa owó lójú méjéèjì, o ò ní gbádùn ara ẹ, àjọṣe ẹ pẹ̀lú àwọn míì sì lè bà jẹ́. Máa rántí pé ẹ̀mí ju owó lọ.
ÀWỌN ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ MÍÌ
Ka Bíbélì lórí ìkànnì, ó wà ní ọgọ́rọ̀ọ̀rún èdè lórí jw.org
MÁ ṢE FI ÀKÓKÒ ÀTI OWÓ ṢÒFÒ LÓRÍ OHUN TÍ KÒ NÍ LÁÁRÍ.
“Ọ̀mùtí àti alájẹkì yóò di òtòṣì, ìtòògbé yóò sì sọni di alákìísà.”—ÒWE 23:21.
MÁ ṢE MÁA RONÚ JÙ NÍPA OWÓ.
“Ẹ yéé ṣàníyàn nípa ẹ̀mí yín, ní ti ohun tí ẹ máa jẹ tàbí tí ẹ máa mu tàbí nípa ara yín, ní ti ohun tí ẹ máa wọ̀.”—MÁTÍÙ 6:25.
MÁ ṢE ÌLARA ẸNIKẸ́NI.
“Onílara èèyàn ń wá bó ṣe máa di olówó, kò mọ̀ pé òṣì máa ta òun.”—ÒWE 28:22.