Àǹfààní Tí Ikú Jésù Ṣe Wá
Lẹ́ẹ̀kan lọ́dún, àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà àti ọ̀pọ̀ àwọn tó bá dara pọ̀ mọ́ wa kárí ayé máa ń ṣe Ìrántí Ikú Jésù bó ṣe pa á láṣẹ. (Lúùkù 22:19) Bá a ṣe ń wá síbi ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì yìí fi hàn pé a mọrírì ohun ribiribi tí Jésù ṣe bó ṣe fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ fún aráyé. Bákan náà, ó máa jẹ́ ká mọ àǹfààní tí ikú Jésù lè ṣe wá ní báyìí àti ní ọjọ́ iwájú.—Jòhánù 3:16.
Kí la lè ṣe ká lè jàǹfààní nínú ikú ìrúbọ Jésù, bóyá a wá síbi ìrántí ikú rẹ̀ àbí a ò ṣe bẹ́ẹ̀? Jésù jẹ́ ká mọ ohun méjì tá a lè ṣe.
1. Kẹ́kọ́ọ̀ nípa Ọlórun àti Jésù. Nígbà tí Jésù ń gbàdúrà sí Bàbá rẹ̀ ọ̀run, ó sọ pé: “Èyí túmọ̀ sí ìyè àìnípẹ̀kun, pé kí wọ́n wá mọ ìwọ Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo àti Jésù Kristi, ẹni tí o rán.”—Jòhánù 17:3.
2. Fi ohun tí ò ń kọ́ sílò. Jésù jẹ́ ká mọ̀ pé ó ṣe pàtàkì ká fi ohun tí à ń kọ́ sílò láyé wa. Bí àpẹẹrẹ, bí Jésù ṣe ń parí Ìwàásù Orí Òkè, ó gbóríyìn fún gbogbo ẹni “tó ń gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ [rẹ̀], tó sì ń ṣe é.” (Lúùkù 6:46-48) Ó tún sọ níbòmíì pé: “Tí ẹ bá mọ àwọn nǹkan yìí, aláyọ̀ ni yín tí ẹ bá ń ṣe wọ́n.”—Jòhánù 13:17.
Ṣé wàá fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ sí i nípa Ọlọ́run àti Jésù? Ṣé wàá fẹ́ mọ bó o ṣe lè fi ohun tí ò ń kọ́ sílò? Wo àwọn ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́.
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì
Bá a ṣe ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́fẹ̀ẹ́ ti ran ọ̀pọ̀ lọ́wọ́ láti lóye ohun tó wà nínú Bíbélì, wọ́n sì ń fi ohun tí wọ́n ń kọ́ sílò láyé wọn.
Lọ sí abala Ẹnì Kan Lè Ràn Ẹ́ Lọ́wọ́ Láti Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.
Wo fídíò náà Ohun Tó O Máa Gbádùn Nínú Ẹ̀kọ́ Bíbélì Rẹ kó o lè mọ bí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.
Ìpàdé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń ṣe ìpàdé lẹ́ẹ̀mejì lọ́sẹ̀ ní àwọn ilé ìpàdé wa. Láwọn ìpàdé yìí, a máa ń jíròrò àwọn ẹ̀kọ́ Bíbélì àti bá a ṣe lè fi wọ́n sílò nígbèésí ayé wa.
Gbogbo èèyàn ló lè wá sáwọn ìpàdé yìí títí kan àwọn tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Tó o bá fẹ́, o lè dara pọ̀ mọ́ wọn lójúkojú tàbí lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì.
Tó o bá fẹ́ mọ ohun tó o máa gbádùn láwọn ìpàdé wa, wo fídíò náà Kí Ló Máa Ń Ṣẹlẹ̀ Nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba?
Tó o bá fẹ́ mọ ibi tá a ti ń ṣèpàdé tó sún mọ́ ẹ, lọ sí abala Ìpàdé Ìjọ Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà.
Àpilẹ̀kọ orí ìkànnì àti fídíò
Ọ̀pọ̀ àpilẹ̀kọ àti fídíò tó wà lórí ìkànnì yìí máa jẹ́ kó o mọ̀ sí i nípa àwọn ẹ̀kọ́ Jésù àti bí ikú rẹ̀ ṣe lè ṣe ẹ́ láǹfààní.
Bí àpẹẹrẹ, tó o bá fẹ́ mọ bí ikú ọkùnrin kan ṣe lè ṣe ọ̀pọ̀ èèyàn láǹfààní, ka àpilẹ̀kọ náà “Báwo Ni Jésù Ṣe Ń Gbani Là?” àti “Kí Nìdí Tí Jésù Fi Jìyà Tó sì Kú?” tàbí kó o wo fídíò náà Kí Nìdí Tí Jésù Fi Kú?