Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Ṣé Èrò Ọlọ́run Ló Wà Nínú Bíbélì?

Ṣé Èrò Ọlọ́run Ló Wà Nínú Bíbélì?

Ohun tí Bíbélì sọ

 Ọ̀pọ̀ àwọn tó kọ Bíbélì sọ pé Ọlọ́run ló darí ohun táwọn kọ sílẹ̀. Wo àwọn àpẹẹrẹ yìí:

  •  Dáfídì Ọba: “Ẹ̀mí Jèhófà ni ó sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ mi, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì wà lórí ahọ́n mi.”—2 Sámúẹ́lì 23:1, 2.

  •  Wòlíì Aísáyà: “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọba Aláṣẹ, Jèhófà àwọn ẹ̀gbẹ́ ọmọ ogun, wí.”—Aísáyà 22:15.

  •  Àpọ́sítélì Jòhánù: “Ìṣípayá láti ọ̀dọ̀ Jésù Kristi, èyí tí Ọlọ́run fi fún un.”—Ìṣípayá 1:1.